آداب السفر وأحكامه
Awọn ẹkọ Irinajo àti awọn ìdájọ rẹ Ọpẹ ni fún Ọlọhun Olúwa gbogbo agbanlaaye, kí ikẹ Ọlọhun àti ọla Rẹ maa ba Anọbi wa Muhammad àti awọn ará ilé rẹ àti awọn saabe rẹ lapapọ.
Awọn ẹkọ Irinajo àti awọn ìdájọ rẹ Ọpẹ ni fún Ọlọhun Olúwa gbogbo agbanlaaye, kí ikẹ Ọlọhun àti ọla Rẹ maa ba Anọbi wa Muhammad àti awọn ará ilé rẹ àti awọn saabe rẹ lapapọ.
Lẹyin naa:
Eleyii ní àkójọ ọrọ ní ṣókí nipa awọn ẹkọ Irinajo àti awọn ìdájọ rẹ, a ṣe igbiyanju lati ṣalaye ọpọlọpọ nkan ti arinrin-ajo ni bukaata si.
Ọlọhun (Allah) ni a nbẹ kí o ṣé ni nkan tí a ṣe nítorí Rẹ nìkan tí a si fi wa ojurere Rẹ, kí o si jẹ kí o wúlò fún apapọ gbogbo Musulumi.
Ìgbìmọ̀ imọ ni ijọ ti n ṣe iṣẹ sin ohun tí wọn kojọ pọ (nipa ẹsin Ìslámù) pẹlú orisirisi ede:
Alakọkọ: awọn ẹkọ Irinajo
O dara fún ẹni tí nṣe Irinajo fún ìjọsìn Hajj tàbí fún awọn ìjọsìn míran kí o ṣe akakun awọn nkan tí nbọ yii:
1. Kí o beere fun ìtọná (istikhaarah) lọdọ Ọlọhun -Ọba mimọ- nipa àkoko, ohun ìgùn, alábàárìn, ati agbegbe ọnà tí awọn ọnà náà bà pọ, kí o si se imọran pẹlu awọn ẹni ti wọn ni iriri ti wọn si jẹ ènìyàn dàada nípa ìrìn-àjò rẹ, sugbọn lilọ sí Hajj tàbí Umrah; méjèejì ni òòrè laisí ìyè méjì nípa rẹ, bí a ṣe ma nṣe ádùá ìtọná (istikhaarah) fún nkan tí o lóore n'ipe: kí o kí ìrun rak'a (opa) méjì lẹyìn náà yiò wà ṣe ádùá tí o wa láti ọdọ Anọbi -kí ikẹ Ọlọhun àti ọlá Rẹ máa ba-.
2. O jẹ ọranyan fún ẹni tí o nṣe ìjọsìn Hajj àti Umrah lọwọ kí o fi (ìjọsìn na) gbèrò ojurere Ọlọhun -tí Ọlá Rẹ ga- àti lati fi sunmọ (Ọlọhun), kí o si ṣọra níbi gbigbero ohun ayé tàbí iṣe iyanran/isakọ, tàbí ero riri orukọ àdàpè, tàbí nítorí sekarimi àti okiki, nítorípé awọn nkan wọn yii yiò jẹ òkùnfà bibajẹ iṣẹ (ìjọsìn) àti àìní gbà wọlé lọdọ Ọlọhun, Ọlọhun tí Ọlá Rẹ ga sọ pé: {Sọ pé: “Emi sa jẹ abara kan bi ti nyin, a ranṣẹ si mi pe Ọlọhun nyin Ọlọhun kanṣoṣo ni. Nitorina ẹniti o ba ngbero lati ba Olúwa rẹ pade, ki o ṣe iṣẹ rere, ki o ma si ṣe fi ẹnikan ṣe orogun ninu ìjọsìn pẹlu Olúwa rẹ̀. (kò gbọ́dọ̀ ṣẹbọ sí Olúwa rẹ̀). [Al-Kahf: 110] O wa ninu hadith qudusi (Ọrọ Ọlọhun tí o mọ): "Èmi Ọlọhun rọrọ kọ já kí nní awọn orogún, ẹnikẹni tí o ba ṣe isẹ ìjọsìn kan tí o wa mú orogún (ẹlomiran) pẹlu mí nínu rẹ, emi yio fí ẹni náà silẹ pẹlu iwa orogún rẹ" [1] [1] Muslim Logba wa pẹlu onka (2985).
3. Ọranyan ní fún ẹni tí n lọ si Hajj àti Umrah kí o kọ ẹkọ (imọ) nípa awọn ìdájọ Umrah àti Hajj, àti awọn ìdájọ ṣíṣe irinajo síwájú kí o to rin, nítorí ki o má ba fí ọranyan (ojuṣe) kan silẹ lalai ṣe tàbí kí o lọ bọ sínú nkan tí a ṣe ni eewọ, Anọbi -kí ikẹ Ọlọhun àti ọlá Rẹ má ba- sọ pe: "ẹnikẹni tí Ọlọhun ba gbèrò oore fún yiò fún ní agbọye (imọ) nipa ẹsin" [2]. [2] Al-Bukhari lo gba wa, pẹlu onka (3116), àti Muslim, pẹlu ouka (100).
4. Ọranyan ni o jẹ fún ẹni tí o fẹ ṣe Hajj tabi Umrah kí o ṣẹṣa yan owo àti dukiya tí o jẹ ẹtọ (Halaali) fún Hajj àti Umrah rẹ, nítorípé Ọlọhun Ọba tí o Mọ ni bẹẹni kòní gbà nkankan ayaafi nkan tí o ba mọ; àtipé owo/dukiya tí o ba jẹ titi eewọ a máa ṣe okunfa kí ènìyàn má ri gbigba adura.
5. Isiwọ kúrò (Ituba) níbi gbogbo iṣẹ ẹsẹ àti ìyapa Ọlọhun, tí o bani awọn abosi àti kudiẹ-kudiẹ lọdọ awọn ènìyàn kí o yáá da ẹtọ wọn padà fún wọn kí o si jẹ kí o kúrò ní akata rẹ, ki baa jẹ ẹtọ tí o rọ mọn ijẹ ọmọluabi wọn tàbí owo (dukiya) tàbí nkan míran.
6. A nfẹ fún onirinajo kí o kọ ìwé asọsilẹ rẹ kalẹ, àti awọn nkan tí o ní àti èyí tí awọn eniyan ni lọdọ rẹ, Anọbi -kí ikẹ Ọlọhun àti ọla Rẹ máa ba- sọ pé: "ko lẹtọ fún ẹnikankan tí o jẹ Musulumi ti o ní nkán kan tí o yẹ ko sọ asọsilẹ nípa rẹ tí yóò sun orun ọjọ méjì ayaafi kí àsọtẹlẹ rẹ wa ni akọsilẹ ni ọdọ rẹ" [3] Kí o sì fi ènìyàn ṣe ẹlẹri sí, bẹẹ kí ó sì san gbogbo gbèsè tí ó wa lọrun rẹ, kí ó tún da gbogbo ohun ìfipamọ́ padà fún àwọn ẹni o ni wọn, tàbí kí o gba iyọnda lọdọ wọn láti jẹ kí o wa lọdọ rẹ. [3] Al-Bukhari lo gba wa, pẹlu onka (2738), àti Muslim pẹlu onka (1627).
7. A fẹ fún oniriajo kí o gbiyanju láti ṣẹṣa alabarin rere kí o si gbiyanju pé kí wọn jẹ ninu awọn akẹkọ imọ ẹsin, dájúdájú eleyii wa nínú òkùnfà ti o fi ṣe kongẹ daada àti kí o má kosi inu àṣìṣe lórí irinajo rẹ, àti níbi ìṣe Hajj rẹ ati umrah rẹ; nítorí ọrọ Anọbi -kí ikẹ Ọlọhun àti Ọla Rẹ máa ba- tí o sọ pé: "Ọmọ ènìyàn yóó má bẹ lórí ìlànà ẹṣin ọrẹ rẹ, kí ẹni kọkan yin yáá wo ẹni tí yóò Yan ni ọ̀rẹ́ rẹ" [4]; Àti nítorí ọrọ Anọbi -kí ikẹ Ọlọhun àti ọlá Rẹ máa ba- tí o sọ pé: "Má ṣe ba ẹnikan ṣe ọrẹ bí kò ṣe ẹni tí o jẹ onigbagbọ ododo, bẹẹ ẹnikan kò gbọdọ jẹ ounjẹ rẹ bí kò ṣe olubẹru Ọlọhun" [ 5]. [4] Abu Daud lo gba wa pẹlu onka (4833). [5] Abu Daud lo gba wa pẹlu onka (4832), àti At-tirmidh, pẹlu onka (2395).
8. A fẹ fún onirinajo pé kí o dagbere fún awọn ará ile rẹ, àti awọn ẹbi rẹ, àti awọn alabagbe rẹ, àti awọn ọrẹ re, Anọbi -kí ikẹ Ọlọhun àti ọla Rẹ máa ba- sọ pé: "ẹni tí o ba fẹ rin irinajo kí o sọ fún awọn tí yio fi silẹ pé: Mo fí yin le Ọlọhun lọwọ, Ẹni (Ọlọhun) tí òhun ti a ba fisọ kii rare" [6[, Anọbi -kí ikẹ Ọlọhun àti ọlá Rẹ máa ba- a máa ki awọn saabe rẹ nígbàtí ọkan nínú wọn ba fẹ rin irinajo, a si máa sọ pé: "Mo fí ẹṣin rẹ ati awọn gba fí pamọ rẹ ati aṣe parí iṣẹ rẹ le Ọlọhun lọwọ" [7] Bẹẹ ni Anọbi -kí ikẹ Ọlọhun àti ọlá Rẹ máa ba- a máa sọ fún ẹni tí o ba tọrọ ki o sọ asọtẹlẹ fún òun nínú awọn onirinajo pe: "Ọlọhun yiò Pese ìbẹrù Rẹ fún ọ, yiò ṣe aforiji ẹsẹ rẹ, yio sí ṣe òòrè fún ọ nirọrun ní ibikíbi tí o bá wà" [8] Arákùnrin kàn tí o fẹ rin irinajo wa sí ọdọ Anọbi kí -ikẹ Ọlọhun àti ọlá Rẹ máa ba-, ni o ba s'ọpe: irẹ ojisẹ Ọlọhun sọ asọtẹlẹ fún mí, Anọbi -kí ikẹ Ọlọhun máa ba- si sọ Fún pé : "Mo n ṣe isiti fún ọ pé kí o bẹrù Ọlọhun, kí o sí máa gbé títóbi Fún Un ní gbogbo òke gegele ti o ba de" nígbàtí o wa lọ tan, ni Anọbi tún sọ pé: "Mo pe Irẹ Ọlọhun bámi kalẹ ko fún, kí O sí ṣe irinajo ni irọrun fún" [9]. [6] At-Tobrani lo gba wa, pẹlu onka (823). [7] Ahmad lo gba wa nínú tira Musnad rẹ, pẹlu onka (4524). [8] At-tirmidhi lo gba wa, pẹlu onka (3444). [9] Ahmad lo gba wa nínú Musnad rẹ pẹlu onka (9724).
9. Kí o ma ṣe mu agogo tabi agidigbo tabi ajá lọwọ l'orí irinajo, nítorí ọrọ Anọbi tí Abu huraira gbawa -kí Ọlọhun yọnu sí- ti o sọ pe dájúdaju òjíṣẹ Ọlọhun -kí ikẹ Ọlọhun àti Ọlá Rẹ má bà- sọ pé: "Awọn malaika wọn kii wa pẹlu awọn ikọ kankan tí àjà tabi agogo ba wa pẹlu wọn" [10]. [10] Muslim lo gba wa, pẹlu onka ( 2113) .
10. Tí o ba fẹ rin irinajo pẹlu ọkan nínú awọn aya rẹ̀ bí ó bá ní ju aya kan lọ, yóò ṣe ìdíje yíyan ẹnikan láàrin wọn (nipasẹ ibo), aya tí ìbo bá ṣubú sórí rẹ̀ ni yóò bá a lọ, Eleyi da lórí hadithi ti A’ishah -kí Ọlọhun yọnu sí- gbà wa, o s'ọpe: "òjíṣẹ Ọlọhun -kí ikẹ Ọlọhun àti ọlá Rẹ máa ba- a má ṣe ìdíje (ibo) láàrin awọn àya rẹ nigbati o ba fẹ rin irinajo, èyíkéyì àya tí ìbo bá ṣubú sórí rẹ̀ ni yóò ṣẹ Irinajo pẹlu Anọbi". [11] . [11] Al- Bukhari lo gba wa, pẹlu onka (2593), àti Muslim, pẹlu onka (2770).
11. A fẹ fún un láti jáde fún Irinajo ni ọjọ (Alamisi) ni ìbẹrẹ ọjọ tí o ba rọrùn fún un, nítorípé Anọbi -kí ikẹ Ọlọhun àti Ọlá Rẹ má bà- máà n ṣe bẹ. Ka'ab ọmọ Maalik -kí Ọlọhun yọnu sí- sọ pé: "O kere nínú awọn ìgbàtí òjíṣẹ Ọlọhun -kí ikẹ Ọlọhun àti ọlá Rẹ má bà- tí yóò ba jáde fún Irinajo kan ayaafi kí o jáde ni ọjọ Alamisi" [12]. [12] Al-Bukhari lo gba wa, pẹlu onka (2949).
A fẹ fún onirinajo kí o ṣe ádùrá tí Ijade kúrò ninú ile nígbàtí o ba fẹ ṣe irinajo tàbí Ijade míràn, kí o wa sọ nígbàtí o ba fẹ jáde ninu ile pe: "(Mo n jáde) pẹlu orúkọ Ọlọhun, mo ba Ọlọhun duro, kòsí ọgban kan, bẹẹni kòsí agbára lẹyin Ọlọhun, Mo sadi Iwọ Ọlọhun kuro nibi ki n sina, tabi ki a si mi lọna, tàbí kí n dẹsẹ, tàbí ki a mu mi dẹsẹ; ati nibi ki n ṣe abosi fún ẹnikan tàbí ki a ṣe abosi fún mi, ati nibi kí n si iwa hu, tàbí kí a o mu mi sí iwa hu" [13] [13] Abu Daud l'o gba wa, pẹlu ouka (5094).
13. A fẹ fún un pé kí o ṣe ádùá irinajo nígbàtí o ba gùn nkan igùn rẹ, tàbí ọkọ rẹ, tàbí ọkọ ofurufu, tàbí awọn nkan rinṣẹ míran, yóò sọ pé: Ọlọhun L'o tobi julọ, Ọlọhun L'o tóbi julọ, Ọlọhun L'o tóbi julọ, lẹyìn náà yóò sọpe: [Mimọ ni fún Ẹni tí O tẹ eleyii lori ba fún wa, bẹẹ sí ní àwa kòní agbára láti tika ara wa tẹ ẹ lori ba, Dajudaju ọdọ Olúwa wà ní ibupadà sí wa} [Az-zuhruf : 14], Iwọ Ọlọhun Ọba, a n tọrọ lọdọ Rẹ pe ki O fún wa ni dààdaà àti ìpaya Rẹ lori irin-ajo wa yii, ki O si fún wa ni iṣẹ tí O yọnu sí ṣe, Iwọ Ọlọhun, se irin-ajo wa yí nirọrun fún wa, si ba ni kà jijinna rẹ kò, Ọlọhun Ọba, Iwọ l'O N bẹ pẹlu wa lórí Irinajo yii, Iwọ náà sí ní Oluwole de ni lori awọn ará àti ẹbi wa, mo n fi Ọ wa isadi níbi isoro[14] irin-ajo, àti nibi riri ohun ti riri rẹ a maa ko ìbànújẹ ba eni[15], àti nibi apadasi-ibu[16] lára nnkan-ini mi ati ebi mi"[17] . Wa'thaaus-safar ni: isoro àti idaamu àti ilekoko Irinajo. Al- Ifsahu 'an Ma'ani-S-sihau (4/284). [15] irisi tí kò dara àti idaranu latara ìbànújẹ. Al-Ifsahu 'an Ma'ani-S-sihau (4/284). [16] (Al-Munqalib) ohun ni: idari padà. Al-Ifsahu 'an Ma'ani-S-sihau (4/284) . [17] Ahmad l'o gba a wa nínú tira Musnadi rẹ, pẹlu onka (6374).
14. A fẹ fún un pé kí o má ṣe da rin irin-ajo lohun nìkan lai sí alabarin pọ, nítorí ọrọ Anọbi -kí ikẹ Ọlọhun àti ọlá Rẹ má bà-: "To ba ṣe pe awọn eniyan mọ ohun tí mo mọ nipa ki ẹni kan o maa da rin, arin irin-ajo kankan o ba ti da rin loru lohun nìkan" [18]. [18] Al-Bukhari lo gba a wa, pẹlu onka (2998).
15. ki awọn oni irinajo o yan ọkan lara wọn gẹ́gẹ́ bí asiwaju; kí o lè se wọn lọ̀kan, kí o sí le mú wọn ní ifi-ẹnu ko, àti kí ó túbọ̀ mú kí wọ́n lè ṣàṣeyọrí nínú ètò àti èrò wọn, Anọbi -kí ikẹ Ọlọhun àti ọlá Rẹ máa ba sọ pé-: "Tí awọn (eniyan) mẹta ba jáde fún irin-ajo kí wọn o yáá yan ẹnikan ni olórí (Asiwaju) larin wọn" [19] . [19] Abu Daud l'o gba wa, pẹlu onka (2608).
16. Kí o gbiyanju láti máa ṣe ohun tí Ọlọhun ṣe ni ọranyan fún ní ti sise awọn ohun ti Ọlọhun pa l'aṣẹ àti ijina sí awọn ohun tí a ṣe leewọ, kí ò sì máa hù awọn ìwà tó dara, kí ó sì máa ràn àwọn tí ó nílò ìrànlọ́wọ́ àti ìtìlẹ́yìn lọwọ, kí o sí máa nan ìmọ fún ẹni tí nwa imọ àti ẹni tí ní nílò rẹ, kí o jẹ olutọrẹ (oninu-rere) pẹlu dukiya rẹ, ti yoo máa ná (dukiya na) síbi aafani ará rẹ ati aafani awọn ọmọ iyà rẹ ati awọn bukata wọn .
17. O dara fún ki o mu owo ati awọn ohun èlò ìrìn-àjò pupọ lọwọ, nítorípé o seese kí inílò rẹ ba lojiji, tàbí kí awọn nnkan yi pada.
18. O dara kí o jẹ ẹni tí o maa tujuka níbi gbogbo nkán wọn yii, ki ọkan rẹ o dà/ma, ki o jẹ oluṣoju-kokoro (olugbiyanju) láti máa mú inú awọn ikọ alabarin rẹ dùn, kí o lè jẹ ẹni tí wọn yoo fẹ́ràn, tí ohun na yoo sí ba wọn rẹ papọ.
19. O dara fún kí o ní ifarada (suuru) lórí ìwà aagọ tí o ba wa láti ọdọ awọn ikọ irin-ajo rẹ, àti ìyapa wọn sí irori rẹ, ki o sí máa ba wọn lo pẹlu (iwa) ti o daa, kí o le jẹ ẹni ọọwọ láàrin wọn, ẹni pataki nínú ẹmi wọn.
20. A fẹ fun awọn oní-rinàjò ti wọn ba sọ sí àyè kan pe kí wọn parapọ sí oju kan, o ṣelẹ pe awọn apakan ninu awọn saabe Anọbi -kí ikẹ Ọlọhun àti ọlá Rẹ má bà- nwọn a maa fanka sí inu awọn oke àti inú awọn ọgbun nigbati wọn ba sọ si àyè kan lori ajo, ni Anọbi -kí ikẹ Ọlọhun àti ọlá Rẹ má bà- wa sọ pé: "Dájúdaju fifanka yín sínú awọn òke àti awọn ọgbun láti ọdọ eṣu loti wa" [20], Lẹyìn èyí, ni nwọn bẹẹrẹ si ni darapọ mọ arà wọn débi pé tí a ba tẹ aṣọ le wọn lórí yóò bo gbogbo wọn pọ. [20] Ahmad l'o gbaa wa nínú Musnadi rẹ, pẹlu onka (17736).
21. A fẹ pé tí o ba sọ sí àyè kan lori ajo tàbí nnkan miiran kí o ṣe ádùá tí o fẹṣẹ rinlẹ láti ọdọ Anọbi kí ikẹ Ọlọhun àti ọlá Rẹ má bà: " Mo n fi awọn gbólóhùn Ọlọhun tí wọn pé wa isàdi níbi aburú ohun tí O da" [ 21]; dajudaju tí o ba sọ eleyii nkán kan ò ní ṣe laburu titi yóò fí kúrò ní àyè yẹn. [21] Muslim lo gba wa, pẹlu onka (2708).
22. A fẹ fún pé kí o ma gbé Ọlọhun tóbi nigba ti o ba n gùnke (awon aye giga), kí o sí máa ṣé afọmọ fún Un nigba ti o ba n sọkalẹ sí ìbi tí o tẹ pẹrẹsẹ, àti awọn isalẹ ọgbun, Jaabir kí Ọlọhun yọnu sí sọ pé: "Awa a ma gbé Ọlọhun tóbi -ALLAHU AKBAR- nigbati a ba n gunke, a si maa se afọmọ fún Un -SUBHANA-LLAH- nigba ti a ba sọkalẹ -lati aye giga-" [22], Wọn kii gbé òun sọke pẹlu gbigbé Ọlọhun tóbi, òjíṣẹ Ọlọhun -kí ikẹ àti ọlá Rẹ má bà- sọ pé: "Ẹ̀yin ènìyàn, ẹ rọra fún ara yín -ẹ ṣe Ohùn yín ni pẹlẹ-, nítorípé kii ṣe odi tàbí ẹni tí kò sí ni ẹ npe, dájúdájú O wa pẹlu yín, dájúdájú Olùgbọ́rọ ti O si súnmọ́ ni nni" [23]. [22] Al-Bukhari lo gba wa, pẹlu onka (2994). [23] Al-Bukhari lo gba wa pẹlu onka (2993).
23. A fẹ fún un pé kí o rìn irin-ajo rẹ ni òru; pàtàkì jùlọ ni ibẹrẹ òru; nítorí gbolohun Anọbi -kí ikẹ Ọlọhun àti ọlá Rẹ má- bà tí o sọ pé: "Ẹ máa fi alẹ́ (oru) rìn, nítorí pé dájúdájú wọn a máa ka ilẹ kò ni òru" [24]. [24] Abu Daud lo gba wa, pẹlu onka (2571).
24. A fẹ fún pé kí o máa se ádùá lọpọ lọpọ lórí irin-ajo; nítorí ọrọ Anọbi -kí ikẹ Ọlọhun àti ọlá Rẹ má bà- tí o sọ pé: "Ádùá mẹta kan tí kii salai gbà kòsí ìyè méjì nípa rẹ: ádùá ẹni tí a ṣe abosi fún, àti ádùá arìnrìn-àjò, àti ádùá obì lori ọmọ rẹ" [25]. [25] Ahmad lo gba wa nínú tira Musnadi rẹ, pẹlu onka (10771).
***
Ẹlẹkeji: imọra lorí irin-ajo
Ọranyan ni fún onirinajo láti ṣe akakun imọra àti ìmọ́tótó ará rẹ, kí o maa ṣe aluwala fún ẹgbin kékeré, kí o sí maa wẹ (ghuslu) fún ẹgbin nla (janabah).
Tí kò bà rí omi, tabi ti omi tí o wa pẹlu rẹ kere tí o sí nílo fun jíjẹ àti mímú rẹ, nigba naa yóò se aluwala oniyẹpẹ (Tayammum).
Bí a se máa n ṣe aluwala oniyẹpẹ ni: kí o fi ọwọ rẹ mejeji lu ilẹ, lẹyin naa ki o fi wọn pa ojú rẹ ati atẹlẹwọ rẹ méjèjì.
Àti pé imọra aluwala oniyẹpẹ imọra tí o ní àsìkò ni, gbogbo ìgbà tí a ba tí rí omi; aluwala oniyẹpẹ tí bajẹ, o si di ọranyan láti lo omi, tí o ba ṣe aluwala oniyẹpẹ fún ẹgbin nla (janaba) lẹyìn náà ti o wa rí omi o di ọranyan fún kí o fi omi wẹ (ghuslu), tí o ba ṣe aluwala oniyepẹ fún imọra ni bí ìgbansẹ lẹyìn náà ti o wa rí omi, o di ọranyan fún lati ṣe aluwala pẹlu omi, o wa nínú ọrọ Anọbi pe: "oun aluwala ni iyepẹ (iyanrin) mimọ jẹ fún musulumi kódà bí kò ba ri omi fún odún mẹwàá, ṣùgbọ́n nigba-kigba tí o ba wa ri omi kí o yáá bẹrù Ọlọhun, kí o si fí omi ba ará rẹ" [26]. [26] Al-Bazar lo gba wa nínú Musnadi rẹ, pẹlu onka (10068).
Fífi ọwọ pa bàtà aláwọ̀ (khuff) -fun aluwala- jẹ ohun ti o ba ofin ẹsin mu, pẹlu ẹri nínú Al-Qur'an, àti Sunnah, àti ipanupọ awọn olutẹle ìlànà Anọbi (Ahulus-Sunnah).
A ṣe agbekalẹ awọn majẹmu kan lórí fífi ọwọ pá bàtà alawọ ti ko ni itilẹ àti awọn nkan tí o tún ri bẹ:
1. Kí bàtà aláwọ̀ tí koni itilẹ tàbí ibọsẹ méjèjì náà jẹ eyii tí o tọ tí o sí mọ.
2. Kí o wọ méjèjì lori ìmọtoto.
3. Kí méjèjì bo ayé tí o jẹ ọranyàn.
4. Kí o jasi pe fífi ọwọ pa lori ẹgbin kékeré ni, nitorinaa kò tọ láti fí ọwọ paa lori ẹgbin nla (janabah), àti lori ohun tí nsọ iwẹ dì ọranyan.
5. Kí fífi ọwọ paa naa wa ye nínú odiwọn akokò ti a la kalẹ ninu òfin ẹṣin (sharia), ti i ṣe ọjọ kàn pẹlu òru rẹ fún ẹni to wa n'ile, bẹẹ ni ọjọ mẹta pẹlu òru rẹ fún onirinajo, akokò yii yóò máa bẹrẹ kété lẹyìn tí a fí ọwọ pàá tan lẹyìn ẹgbin kékeré, yóò sí parí lẹyin wákàtí mẹrin le lógún fún ẹni tí o wá n'ile ti ko lọ bikan, wákàtí mejile laadọrin fún onirinajo.
Fífi ọwọ pá bàtà aláwọ̀ tiko ni itilẹ tàbi ibọsẹ yóò máa bàjẹ pẹlu ọkan nínú nkán mẹta:
1. Ti nnkán tí o le sọ iwẹ dì ọranyan ba ṣẹlẹ, gẹgẹ bi ẹgbin nla (janabah) fífi ọwọ paa tí bajẹ o si di dandan kí a wẹ (ghuslu).
2. Tí o ba yọ wọn (lese) lẹyìn tí o tí paa méjèjì.
3. Tí àkokò tí a gbà wọlé nínú òfin ẹṣin ba ti pé fifi ọwọ pàá tí bajẹ.
***
Ẹlẹkẹta: Awọn ìdájọ dindin irun kù ni orí ajo:
Dindin irun kù lórí irin-ajo ni o dára jù kí a ki i pe lọ, ṣugbọn tí arin-ajo ba kí irun ọlọpa mẹrin ni mẹrin, irun rẹ ni alaafia ṣugbọn o ya pa sí ohun tí o dára jùlọ.
Onirinajo yóò má din irun ku nígbàtí o ba tí jáde kúrò l'ára gbogbo awọn ile ileto rẹ tàbí ìlú rẹ, eleyii ni ibiti ọgọrọ nínú awọn oní mimọ tẹle.
Tí o ba ṣe irin-ajo lẹyìn tí àsìkò irun tí wọlé o le din Irun náà kù; nítorípé o tí ṣe irin-ajo síwájú kí asiko irun náà o to kọja.
Ṣugbọn ẹẹri kí-kí irun ayila (irun ọsan) papọ mọ irun irọlẹ (Alasari), tàbí irun aṣalẹ (Magrib) papọ mọ irun akisun (Ishai) Sunnah ni fún onirinajo nígbàtí o ba ni bukata sí, tí irinajo bà le gan, tí onirianjo si n tẹ siwaju ninu irin rẹ (ti ko duro), yóò wà ṣẹ ohun ti yóò rọrùn julọ fun un, yala ki o ki ìrun (meji) papọ ni àkoko akọkọ, tàbí ki o lọwọn lara de àkokò to kẹyin.
Ṣugbọn tí o ba ṣe pe onirinajo kòní bukaata sí láti pa irun méjì pọ kòní pàá pọ, gẹgẹ bi kí o sọ sí ààyè kan ti ko si wu u láti fí ibẹ silẹ ayaafi lẹyìn ti asiko irun kejì ba wọlé, ohun ti o dara ju ni ki o ma ki irun meji pọ; nitoripe ko nilo si, nítorí idi eyii si ni Anọbi -kí ikẹ Ọlọhun àti Ọlá Rẹ má bà- o ṣe ki irun meji papọ nigbati o sọ si mina ni Hajji idagbere; nitori ai ni ilo si.
Ṣugbọn irun tí o jẹ akigbọrẹ (èyí tí kii ṣe ọranyan) onirinajo yóò máa kí irun aki gbọrẹ bí ẹni ti o wa nile máa ṣe nki, nitori na; yóò maa kí Naafilah àsìkò iyalẹta àti (Naafilah) òru, àti witir àti awọn Nafilah miran yatọ si awọn Nafilah tí o sọ mọ irun ayila (Zuhri), àti (Magrib) àti (Isha'i), èyí to wa nínú ìlànà Anọbi ni pé ko ni kí awọn eyun ni.
O dá kí a kí irun aki-gbọrẹ lórí nkán gùn lorí irin-ajo: bí ọkọ òfurufú, tàbi ọkọ ayọkẹlẹ, tàbi ọkọ oju-omi, àti awọn nkan rinṣẹ míran, ṣugbọn nipa irun ọranyan dandan ni ki a sọkalẹ láti kí ayaafi ti idiwọ ba wa.
Irun onirinajo lẹyìn ẹni tí o wa n'ile ninu ilú lalaafia, onirinajo yóò kí irun rẹ pé gẹgẹ bí tí Imamu rẹ, yala o ba gbogbo irun ni tàbí ọpa (raka) kan tabi nkan to kéré si ọpa (rakah kan), débi pé tí o ba wọ irun pẹlu imam níbi gbólóhùn ijẹri (ataaya) to gbẹyin síwájú kí a to salama, sibẹ náà yoo kí irun rẹ lakipe, eleyii ni o se deede nínú ọrọ awọn oní mimọ.
***
Ẹlẹẹkẹrin: awọn ẹkọ ìdarí padà wa sile láti Hajj àti Umrah tàbí irin-ajo
O dara fún kí o tètè pa si ile kí o sí má pẹ lórí ajo lai sí idiwọ kan to mú pẹ, nítorí ọrọ Anọbi -kí ikẹ Ọlọhun àti ọlá Rẹ má bà- tí o sọ pe: "Egige kan nínú ìyá ni irin-ajo jẹ, ó máa ń dí eniyan lọwọ kúrò nibi jijẹ, mimu ati ibusun (oorun) rẹ̀, tí eniyan bá ti parí ohun tí ó lọ ṣe, kí ó ya yara padà lọ sí ilé lọ́dọ̀ àwọn ará ilé rẹ̀" [27] . [27] Al- Bukhari lo gba wa, pẹlu onka (1804), àti Muslim pẹlu onka (1927).
Tí o ba fẹ padà sí ìlu rẹ o ní láti ka adua irinajo nígbàtí o ba fẹ gùn nkán gùn rẹ, yóò wa tún ṣe afikun pe: "a padà dé, a n ronupiwadà lọ si ọdọ Ọlọhun, a si n jọsìn fún Ọlọhun, a sí n fi ọpe fun Oluwà wa nikan" [28]. [28] Al-Bukhari lo gba wà, pẹlu onka (1797), àti Muslim, pẹlu onka (1342).
A fẹ fún pe nìgbà tí ba ndari padà láti irinajo rẹ ki o ma sọ ohun to fẹsẹ múlẹ dàda láti ọdọ Anọbi -kí ikẹ Ọlọhun àti ọlá Rẹ má bà- òun n'ipe tí o bari láti oju ogun, tàbí Hajj tàbí umrah ,aa máa gbé Ọlọhun tóbi (ALLAHU AKBAR) ní gbogbo ibí gíga lórí ilẹ lẹmẹẹta lẹyìn náà yóò wà s'ọpe: "Kò sí Ọba kan tí o tọ lati fi ododo jọsin fún yatọ si Ọlọhun Ọba nìkan ṣoṣo, Kò sí orogún fun Un, Oun l'O ni akoso ati ọpẹ, Oun sí ní Alágbara lórí gbgbo nnkán, a padà dé, a n ronupiwadà lọ si ọdọ Ọlọhun, a si n jọsìn fún Ọlọhun, a sí n fi ọpe fun Oluwà wa nikan, Ọlọhun mu adehun Rẹ sẹ, O sí se aranṣe fun ẹrú rẹ, O si sẹgun awọn ijọ alaigbagbọ l'Oun nikan ṣoṣo" [29]. [29] Al-Bukhari lo gba wa, pẹlu onka (4116).
A fẹ fún pé tí o ba tí fojú kan ìlú rẹ kí o sọ pé: "a padà dé, a n ronupiwadà lọ si ọdọ Ọlọhun, a si n jọsìn fún Ọlọhun, a sí n fi ọpe fun Oluwà wa nikan" [30], tí yóò si ma paara rẹ títi yóò fí wọ ìlú rẹ, nítorípé Anọbi -kí ikẹ Ọlọhun àti ọlá Rẹ má bà- ṣe bẹẹ. [30] Al-Bukhari lo gba wa, pẹlu onka (1797), àti Muslim, pẹlu onka (1342).
Kí o má dari wọlé ba awọn ará ile rẹ ní òru lai sí idi to ba jẹpé o tí pẹ ti o tí fí ile silẹ ayaafi kí o jasi pe o tí sọ fun wọn ti, tí o sí sọ àkókò tí yóò dárí ni òru fun wọn, nitori pé Anọbi -kí ikẹ Ọlọhun àti ọlá Rẹ má bà- kọ eleyii (fun wa), Jaabir ọmọ Abdullahi -kí Ọlọhun yọnu sí awọn méjèjì- sọ pé: "Òjíṣẹ Ọlọhun -kí ikẹ Ọlọhun àti ọlá Rẹ má bà- kọ kí eniyan o maa fi oru wọle ba awọn ará ile rẹ" [ 31]. Nínú ọgban àti òye tí o wa níbẹ ni ohun tí ẹgba wa miiran ṣalaye pe: “títí obìnrin tí irun rẹ ti dàrú yóò fi tún irun rẹ̀ (ṣe) [32], àti títí obìnrin tí (ọkọ rẹ) ti pe laajo yóò fi gé irun ara rẹ̀ (yoo fi tun ara rẹ ṣe)” [33], nínú ẹgba wa míràn: "Òjíṣẹ Ọlọhun -kí ikẹ Ọlọhun àti ọlá Rẹ má bà- kọ fun ọkunrin (ọkọ) lati maa fi oru wọle tọ awọn ará ile rẹ,nítorí kí ó má bà a jẹ bí ẹni pé ó ń fura sí wọn (pe boya wọn n ṣe ijamba rẹ), tàbí ki o maa wá awọn àṣìṣe wọn" [ 34]. [ 31] Muslim lo gba wa, pẹlu onka (715). [32] (Assa'itha) ni: Obìnrin tí o tí lo ipara tàbí ti o ti ya irun rẹ tipẹ, (Al-istidad) ni: lilo ìrìn (àbé), ( Al-Mugibah) ni: obìnrin tí ọkọ rẹ kòsí nílé. Tira: At-Tahreer Fí Sharih Sahih Muslim - Al-Asbahaaniy (Ojú ewé 292). [33] An-Nasa'i lo gba wa, pẹlu onka (9099). [34] Muslim lo gba wa, pẹlu onka (715).
A fẹ fún ẹni tí n ti irinajo bọ kí o bẹrẹ pẹlu masalasi tí o sunmọ ile rẹ, kí o si k'írun ọpa (raka'a) méjì ninu rẹ, nítorípé Anọbi -kí ikẹ Ọlọhun àti ọlá Rẹ máa ba- se bẹ .
A fẹ fún onirìn-àjò, nígbà tí ó bá padà láti ìrìn-àjò, kí ó hùwà pẹ̀lẹ́pẹ̀lẹ́ sí àwọn ọmọ kékeké nínú ẹbí rẹ̀ àti àwọn aládùúgbò rẹ̀, kí ó sì ṣe dada sí wọn bí wọ́n bá pàdé e nígbà tí ó dé, láti ọdọ ọmọ Abass -kí Ọlọhun yọnu sí awọn méjèjì- o sọ pe: nígbàtí Anọbi -kí ikẹ Ọlọhun àti ọlá Rẹ máa ba- dé si Makkah awọn ọmọ kékèké ìdílé Abdul-Muttalib sáré lọ pàdé rẹ, ní o ba gbé ọkan siwaju re òsì gbé ikeji sí ẹyin rẹ, ni Abdullahi ọmọ Ja'far -kí Ọlọhun yọnu sí- bà sọ pé : "Ti Òjíṣẹ Ọlọhun -kí ikẹ Ọlọhun àti ọlá Rẹ má bà- ba de de láti irinajo kan, wọn a maa gbe wa lọ pade rẹ, o wa sọ pé: wọn si gbe emi àti Hassan tàbí Husain lọ pade rẹ (Anọbi) ni ọjọ kan, ni Anọbi ba gbe ọkan nínú wa síwaju rẹ, o si gbe ẹnikeji sí ẹyin rẹ titi ti afi wọ Madinah" [35]. [53] Musilim lo gba wa, pẹlu onka (2428).
A fẹ (fun onirinajo) lati funni ni ẹbun, nítorí pé ẹbun ma n mú inú-dídùn wá sí ọkàn, a si maa yọ ìkórìíra kúrò, bẹẹ ni a fẹ kí a gbà ẹbùn tí wọn ba fun wa, ki a si s'ẹsan lóri rẹ (pẹ̀lú ìdúpẹ́ tàbí dada míràn), A si kórìíra kí a kọ ẹbun lai sí ìdí òfin-Ṣarí‘ah to le muni kọ ọ, nítorí eyi ní Anọbi -kí ikẹ Ọlọhun àti Ọlá Rẹ má bà- ṣe s'ọpe : "Ẹ máa fi ẹ̀bùn fún ara yin, ẹ si máa fẹràn ara yin" [36]. Ifunra ẹni l'ẹbun jẹ ọkan nínú awọn òkùnfà tí má nfa ìfẹ ati ìbáṣepọ̀ rere láàrin awọn Musulumi. [36] Al- Bayhaki ló gba wa nínú tira As-sunanil Kubrah, pẹlu onka (11946) .
Nígbati arin-irinajo ba dé sí ìlu rẹ, A nifẹ si kí a kí kaabọ pẹlu didimọ ará ẹni, nitori nkan tí o fidi mulẹ lọdọ awọn saabe Anọbi -kí ikẹ Ọlọhun àti Ọlá rẹ máa ba- gẹgẹ bí Anas -kí Ọlọhun yọnu sí- ṣe sọ: "wọn jẹ ẹni to se pé tí wọn ba pade arawọn wọn; wọn o ba arawọn lọwọ, tí wọn bà si darí láti ajo wọn a maa dimọra wọn" [37]. [ 37] At-Tobaraani lo gba wa nínú tira Al-Aosat, pẹlu onka (97).
Kí Ọlọhun se ikẹ ati igẹ fún Anọbi wa Muhammad.