فضائل وآداب المسجد النبوي

فضائل وآداب المسجد النبوي

Àwọn ọlá àti àwọn ẹ̀kọ́ Masalasi Anọbi, àti àwọn ìdájọ́ ṣíṣe àbẹ̀wò sí saare Anabi - kí ikẹ àti ọlá Ọlọhun máa bá a - àti sí àwọn saare àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀ méjèèjì - kí Ọlọhun yọnu sí wọn.

Language: lang_yo
Prepared by: lÌgbìmọ̀ Ìmọ̀ ní abẹ ìṣàkóso àlámọrí ọ̀rọ̀ ẹ̀sìn ní Masalasi Al-Ḥarām ni Makkah àti Masalasi An-Nabawi ni Modinah.
Version: 1.0
Translations 43
Amharic Assamese Azerbaijani Bengali +39
Attachments 7
PDF
Audio
Video
+3

Àwọn ọlá àti àwọn ẹ̀kọ́ Masalasi Anọbi, àti àwọn ìdájọ́ ṣíṣe àbẹ̀wò sí saare Anabi - kí ikẹ àti ọlá Ọlọhun máa bá a - àti sí àwọn saare àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀ méjèèjì - kí Ọlọhun yọnu sí wọn.

Ìgbéjáde

Ìgbìmọ̀ onímọ̀ ìjìnlẹ̀ lábẹ́ ìdarí ọ̀rọ̀ ẹ̀sìn ní Mọ́ṣáláṣí Haram Makkah àti Mọ́ṣáláṣí Anabi.

1447 A.H

Ọrọ isiwaju

Ọpẹ ni fun Ọlọhun Ọba gbogbo agbaye, ikẹ ati ọla ki ó máa bá ẹni tí a rán ní iṣẹ́ ki ó máa jẹ́ ìkẹ́ fún gbogbo àgbáyé, ikẹ ati ọla naa ki ó máa bá awọn ara ile rẹ ati awọn saabe rẹ (ọmọ lẹyìn rẹ akọkọ) ati ẹni tí ó bá tẹle ìlànà rẹ, tí ó sì mọna pẹlu ìtọ́sọ́nà rẹ titi di ọjọ ẹsan, lẹ́yìn náà:

Eleyi ni àkori ọrọ ní ṣókí, tí ó kó àwọn ọlá pàtàkì ti masalasi Anọbi sínú, àti àwọn ẹkọ ṣíṣe àbẹ̀wò sí i, àti àwọn ẹkọ ṣíṣe àbẹ̀wò sí saare Anọbi, àti saare àwọn saabe Rẹ̀ méjèèjì, kí ìkẹ́ àti ọlà Ọlọ́hun máa bá a, a ṣàá jọ fún àwọn olùṣàbẹ̀wò sí masalasi Anọbi, kí wọ́n lè ní ìmọ̀ àti òye nípa ọlá masalasi Anọbi ummah, kí ìkẹ́ àti ọlà Ọlọ́hun máa bá a, àti àwọn ẹkọ ṣíṣe àbẹ̀wò sí i àti kiki irun nínú rẹ̀, a ń retí lọ́dọ̀ Ọlọhun Alápọnle Olóore pé kí Ó fi ṣe àǹfààní, kí Ó sì ṣe é ní iṣẹ́ rere, kí ó sì jẹ́ nítorí Ojú rere Rẹ̀ nìkan, dájúdájú Òun ni Ẹni tí ó dára jùlọ tí a lè bèrè lọ́wọ́ Rẹ̀, àti Alapọnle jùlọ tí a lè ní ìrètí sí.

Ìgbìmọ̀ onímọ̀ ìjìnlẹ̀

Alakọkọ: Àwọn ọlá mọṣalaasi Anọbi

Ọlọhun - Ọba ti ọla Rẹ ga - sọ bayi pe : «Olúwa rẹ l’Ó ń ṣẹ̀dá ohun tí Ó bá fẹ́. Ó sì ń ṣa (ohun tí Ó bá fẹ́) ní ẹ̀ṣà. Ṣíṣa ẹ̀ṣà kò tọ́ sí wọn. Mímọ́ ni fún Allāhu. Ó sì ga tayọ n̄ǹkan tí wọ́n ń fi ṣẹbọ sí I.» [Al-Qasas: 68] Ati pe Ọlọhun ti yan aaye yii lati jẹ́ mọsalasi fun Anabi Rẹ - ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a-, O si fi ọpọlọpọ ọla dá a yàtọ̀, lára wọn ni:

Dájú dájú Ó jẹ́ ọ̀kan nínú àwọn Mọ́sálásí mẹ́tẹ̀ẹ̀ta tí a le tori rẹ di ẹrù ìrìn-àjò sí:

Lati ọdọ Abu Huraira -ki Ọlọhun yọnu si i-: ó gbé e dé ọ̀dọ̀ Anabi -kí ìkẹ́ àti ọlá Ọlọ́hun máa bá a-: «A kò gbọdọ̀ rin irin-àjò àyàfi lọ sí àwọn mọ́sálásí mẹ́ta: Mọ́sálásí mi yìí, Mọ́sálásí Harami, àti Mọ́sálásí Al-Aqsa» [1]. [1] Bukhōriy ni o gbe e jáde pẹlu ounka (1189), Muslim pẹlu ounka (1397), gbólóhùn náà ti Muslim ni.

Òun ni pe dájú dájú irun ti a ba ki ninu rẹ loore ju ẹgbẹrun irun lọ ti a ki ni ibi ti o yatọ si i afi irun ti a ki ni mọsalasi abeewọ:

Lati ọdọ Abu Hurayra – ki Ọlọhun yọnu si i – dajudaju Anabi – ki ikẹ ati ọla Ọlọhun maa ba a – sọ pe: “Irun kan ti a ba ki ni mọsalasi mi yii loore ju ẹgbẹ̀rún irun ti a ki ni ibi ti o yatọ si i lọ, afi irun ti a ki ni mọsalasi abeewọ”[2]. [2] Bukhōriy ni o gbe e jáde pẹlu ounka: (1190), àti Muslim pẹlu ounka: (1395), gbólóhùn náà ti Bukhōriy ni.

Daju dájú oun ni Pé òun ni mọ́sálásí tí wọ́n fi ìpìlẹ̀ rẹ̀ lélẹ̀ lórí ìbẹ̀rù Allāhu láti ọjọ́ àkọ́kọ́:

Lati ọdọ Abu Sa'eed Al-Khudriy - ki Ọlọhun yọnu si i - o sọ pe: Mo wọle tọ Òjíṣẹ́ Ọlọhun - ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a - ninu ile ọkan ninu awọn iyawo rẹ, ni mo bá sọ pe: Ìwọ Òjíṣẹ́ Ọlọhun, ewo ninu awọn mọsalasi mejeeji ni a fi le'lẹ lori ìbẹ̀rù Ọlọhun? Ni Anabi bá mu ìkunwọ́ kan ninu òkúta wẹ́wẹ́, ó si fi lu ilẹ̀, lẹ́yìn náà, o si sọ pé: “Mọṣalaṣi yín yíì ni” èyí wa fún mọṣalaṣi Mọdinah[3]. [3] Muslim ni o gbe e jade (1398).

Dájú dájú ẹsan ẹni tí n wá ìmọ̀ nínú rẹ̀, ó da gẹ́gẹ́ bíi ẹsan ẹni tí n jagun sí ojú ọ̀nà Ọlọ́hun ni :

Lati ọdọ Abu Hurairah, ki Ọlọhun yọnu si i, o sọ pe: Mo gbọ Ojiṣẹ Ọlọhun - ki ikẹ ati ọla Ọlọhun maa ba a - ti n sọ pe: “Ẹni tí ó bá wá sí mọsalasi mi yii, tí kò wá á àfi fún ire tí yóò kọ́ tàbí tí yóò fi kọ́ ẹlòmíràn, ó wà ní ipò oníjàgbara ní ọ̀nà Ọlọ́hun, àti ẹni tí ó bá wá fún ohun tí ó yàtọ̀ sí ìyẹn, ó dàbí ọkùnrin kan tí ó ń wo ẹrù ẹlòmíràn”[4]. [4] Ibnu Mājah ni o gbe e jáde (227), pẹlu isafiti tí o lalaafia.

Dájú dájú Omí Abata tí o lọla wa níbẹ:

Láti ọdọ Abu Hurayrah - ki Ọlọhun yọnu sí i - lati ọdọ Anabi - kí ikẹ ati ọla Ọlọhun máa bá a - o sọ pe: «láàrin ile mi sí pepele ìdúró sọrọ mí abata kan nínú awọn abata ọgbà idẹra wa níbẹ, àti pé pepele ìdúró sọrọ mi wà lórí adágún-odò mí»[5]. [5] Al-Bukhari lo gba wa, pẹlu onka (1195), àti Muslim, pẹlu onka (1390).

Ẹlẹẹkeji: ninifẹ ṣí siṣe àbẹ̀wò sí masalasi Anọbi olọ́lá.

Nítorí àwọn ọlá wọ̀nyí àti àwọn mìíràn, ni wọ́n se fẹ́ràn ṣíṣe àbẹ̀wò sí masalasi Anọbi láti kirun àti láti ṣe ìjọsìn níbẹ̀.

Ó jẹ́ ìlànà Anọbi fún ẹni tí ó ń ṣe Hajj àti ìjọsìn míràn láti ṣe àbẹ̀wò sí Masalasi Anọbi ṣáájú Hajj tàbí lẹ́yìn rẹ̀, ṣíṣe àbẹ̀wò yìí kò sí nínú àwọn mọ̀jẹmu Hajj, tàbí àwọn òpó rẹ̀, tàbí àwọn ohun tó jẹ́ dandan nínú rẹ̀, kò sì ní àsopọ̀ kankan pẹ̀lú rẹ̀.

- Kò sí iye àwọn irun kan pàtó tàbí iye ìgbà kan pàtó láti lò ní ìlú Mádina gẹgẹ bí monjẹmu fún ṣíṣe àbẹwò Mọsalasi Anabi (ki ikẹ ati ọla Ọlọhun máa bá a), tàbí gbígbé fún àsìkò kan pàtó ní ìlú Mẹdina, kàkà bẹ́ẹ̀ àbẹwò náà á ti wáyé pẹ̀lú kiki irun ẹyọ kan, yálà ó jẹ́ irun ọrọyan ni tàbí ìrun àfìkún, ṣùgbọ́n bí iye àwọn irun tí a kí níbẹ̀ bá ṣe pọ̀ sí i, bẹ́ẹ̀ ni ẹsan náà yóò ṣe pọ̀ sí i.

- Wọ́n fẹ́ fún ẹni tí ó ṣe àbẹ̀wò sí Mọsalasi Anabi kí ó kí gbogbo àwọn ìrun ọ̀ranyàn níbẹ̀ àti bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ àwọn ìrun àfìkún, tii se Nofilah nítorí ohun tí ó ti ṣáájú pé kìkì irun nínú rẹ̀ lóore ju ẹgbẹ̀rún irun lọ ní ibi tí ó yàtọ̀ sí i, àfi Mọsalasi Ọwọ tí o wa ni Makkah.

Ẹlẹẹkẹta: Awọn ẹkọ ṣíṣe àbẹ̀wò sí masalasi Anọbi.

Tí musulumi bá dé masalasi Anọbi, wọ́n fẹ́ kí ó lo àwọn ẹkọ ẹsìn tí ó jẹmọ́ àwọn mọsalasi lápapọ̀, àti masalasi Anọbi ní pàtàkì, àwọn náà ni:

Kí o wá sí máṣálááṣí pẹ̀lú ìdákẹ́jẹ́ẹ́ àti ifarabalẹ, ìmọ́ra, irísí tó rẹwà, àti òórùn dídùn; láti ọ̀dọ̀ Abī Hurayrah - kí Ọlọ́hun yọ́nú sí i-, o ni pé ojiṣẹ́ Ọlọ́hun -kí ìkẹ àti ọlà Ọlọ́hun máa bá a-, sọ wípé: «Nígbà tí wọ́n bá pe Irun, tí wan sí gbe e dúró , ẹ má ṣe sáré wọ irùn, kí ẹ sì wá wọ irùn pẹ̀lú ifọ̀kànbalẹ̀. èyí tí ẹ bá bá, kí ẹ ki í, tí ó bá sì bọ fún yín , kí ẹ pé e. Dájúdájú nígbà tí ẹnikọ̀ọ̀kan yín bá ń gbéra lọ síbi ìrun, ó ti wà nínú ìrun niyẹn»[6]، Láti ọ̀dọ̀ Abu Sa'eed Al-Khudriy- ki Ọlọhun yọnu si i- dajudaju Anabi- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- o sọ pe: «Iwẹ ọjọ Jimoh jẹ dandan lori gbogbo ẹni ti o ti balaga, ki o si fi pako run awọn eyin rẹ, ki o si lo lọ́fíńdà ti o ba ri»[7]، Ati pe obinrin, tí ó bá wá sí Mọ́sálásí, ó jẹ́ dandan fún un kí ó jẹ́ ẹni tí ó bo ara rẹ̀ pẹ̀lú hijabu rẹ̀, kò sì lẹ́tọ̀ọ́ fún un kí ó lo lọ́fíńdà nítorí ọ̀rọ̀ Ànábì - ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a: «Bí obìnrin kan nínú yín bá lọ sí Mọṣalaṣi, kò gbọdọ̀ fọwọ́ kan turare tàbí kò gbọdọ lọ lọfinda»[8]. [6] Bukhari ni o gbe e jade pẹlu ounka (636), ati Muslim pẹlu ounka (602). [7] Wọ́n fara mọ́ ọ, Bukhōriy ni o gbe e jáde pẹlu ounka (846), àti Musilim pẹlu ounka (858), Al-muhtalim sì ni ẹni tó ti balaga. [8] Muslim ni o gbe e jade (443).

Kí a gbé ẹsẹ ọ̀tún wọlé sí inú Mọnsalasi Anọbi, àti ṣíṣe adua wíwọ mọsalasi. Won fẹ kí olùṣe abẹwò wọlé pẹ̀lú ẹsẹ ọ̀tún rẹ nígbàtí o bá wọ inú mọnsalasi anọbi gẹ́gẹ́ bí àwọn mọnsalasi yòókù, àti kí o se adura yíì: «Mo wọ le Pẹlu orúkọ Ọlọhun, ìkẹ́ máa bá Òjíṣẹ́ Ọlọhun, Ọlọhun, forí àwọn ẹ̀ṣẹ̀ mi jìn mí, kí o sì ṣí àwọn ilẹ̀kùn ìkẹ́ Rẹ fún mi»[9]، Bákan náà ni yóò sọ pe: «Mo wa iso pelu Olohun Ọba ti O tobi, ati pelu iwaju Re alaponle, ati agbara Re ti o ti nbẹ tipẹ kuro ni odo shaytaan ẹni ẹkọ»[10]. [9] Ibnu Mājah ni o gbe e jáde (771), pẹ̀lú sanad tí ó ní àlàáfíà. [10]Abu Daa'ud ni o gbe e jade, pẹlu ounka (466), pẹlu iṣẹ afiti tí o lalaafia (sahiiḥ).

Ṣíṣe Irun Kíki Masalaasi: Ó jẹ́ sunna fún ẹni tí ó bá wọ Masalaasi Anabi láti kírun níbẹ̀, pé kí ó kí rakaa méjì ni ti kiki masalaasi síwájú kí ó tó jókòó, láti ọ̀dọ̀ bàbá Qatādah Al-Hārith ọmọ Rib‘iyy Al-Anṣāriyy - kí Ọlọ́hun yọ́nú sí i -, ó ní: Anabi - kí ikẹ́ àti ọlá Ọlọ́hun máa bá a - sọ pé: «Ti ẹnikẹni ninu yin ba wọ masalaasi, ki o ma jokoo titi yio fi ki rakaat meji»[11]. [11] Al-Bukhari lo gba wa, pẹlu onka (1171), àti Muslim, pẹlu onka (714) wàn sí panupọ lórí rẹ.

Níní ìfẹ kíkirun ní àwọn saafu ( titoo lórí ilaa ) àkọ́kọ́; latara ọlá tí o tóbi tí o wá níbẹ, èyí kò sì níí ṣeéṣe àyàfi pẹ̀lú títètè lọ síbẹ̀, fún hadith Abu Hurayrah - kí Ọlọ́hun yọ́nú sí i-: pé dájúdájú Òjíṣẹ́ Ọlọ́hun -kí ìkẹ́ àti ọlá Ọlọ́hun máa bá a- sọ pé: «Tó ba se pé awàn ènìyàn mọ òòrè tí o wa níbi piperun àti tito sí iwájú, lẹ́yìn náà tí wan kò rí ọ̀nà kan àfi kí wan se ifigagbaga lé e lórí, wan baa se bẹ»[12]، Àti nítorí ọrọ anọbi -kí ikẹ Ọlọhun àti ọlá Rẹ máa ba a- tí o sọ fún àwọn sàábà Rẹ -kí Ọlọhun yọnu si wọn- pé: «Ẹ tẹ̀ síwájú kí ẹ sì máa tẹ̀lé mi, kí àwọn tí wọ́n wà lẹ́yìn yín sì máa tẹ̀lé yín, àwọn ènìyàn kan kò níí yéé máa fà sẹ́yìn títí tí Ọlọ́hun yóò fi fà wọ́n sẹ́yìn»[13]. [12] Wọ́n fohùn ṣọ̀kan lé lórí, Al-Bukhari pẹ̀lú onka (615), àti Muslim pẹ̀lú onka (437). [13] Muslim ni o gbe e jade: (438).

Niti awọn obinrin, eyi ti o daa julọ fun wọn ni irun ni awọn saafu( tito ìlà ) igbẹyin, ati jijinna si awọn ọkunrin, nitori hadith bàbá ololongbo kékeré (Hurayrah), kí Ọlọhun yọnu si i, o sọ pé: Ojiṣẹ Ọlọhun -ki ikẹ ati ọla Ọlọhun maa ba a- sọ pé: "Eyi ti o daa julọ ninu awọn saafu ,( tito ìlà fún Irun ) awọn ọkunrin ni akọkọ rẹ, eyi ti o buru julọ ninu rẹ ni igbẹyin rẹ, ati pe eyi ti o daa julọ ninu awọn saafu ( tito kirun ) awọn obinrin ni igbẹyin rẹ, eyi ti o buru julọ ninu rẹ ni akọkọ rẹ"[14], Ṣùgbọ́n tí wọn bá da irun kí lọtọ, tàbí tí gàgá bá wà láàrin wọn àti àwọn ọkùnrin, gẹ́gẹ́ bí ó ṣe rí ní Mọsalasi Anabi, dajudaju eyi ti o daa julọ ninu saafu ( tito ìlà fún Irun ) wọn ni akọkọ rẹ; nitori pe ìdí rẹ̀ ti kúrò. [14] Muslim ni o gbe e jade pẹlu onka (440).

Kikirun lẹyin Imam, ati iṣọra kuro nibi ṣiṣiwaju rẹ; nítorí hadiisi bàbá ololongbo kékeré Hurairah -ki Ọlọhun yọnu si i- pe Anabi -ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- sọ pe: «Wọn gbe imaamu kalẹ lati maa kọṣe rẹ ni»[15]. [15] Bukhari ni o gbe e jade pẹlu ounka (722), ati Muslim pẹlu ounka (417).

Kò yẹ fún olùkírun láti ṣíwájú Imam, ( láti dúró kirun ni iwájú Imam ) àfi ní ìgbà tí bukata ba wa ye fún bí kí mọ́sálásí tí kún fún àwọn olùkírun tó bẹ́ẹ̀ tí kò fi rí ààyè láti kirun àfi níwájú Imam.

Ṣíṣe ojú kòkòrò lórí dídi àwọn ààyè tó ṣí sílẹ̀ láàrin àwọn saafu ( tito ìlà fún irun kìkì) , àti tító wọn, ṣùgbọ́n pẹ̀lú ṣíṣọ́ra kúrò níbi fífún àwọn ènìyàn pọ̀ àti dínà mọ́ wọn, dída ọrùn wọn kọjá, àti rírekọjá níwájú àwọn olùkirun; nítorí pé ìyẹn nmú ni ṣubú sínú ẹ̀ṣẹ̀.

Kíkírun ní ààyè Araodọh ( abata ) Alaponle fún ẹni tí ó bá rọrùn fún bẹ́ẹ̀; nítorí hadíìsì Abu Urairah -kí Ọlọ́hun yọ́nú sí i-, pé Ànábì -kí ìkẹ́ Ọlọ́hun àti ọlá Rẹ̀ máa bá a- sọ pé: «láàrin ile mí sí pepele ìdúró sọrọ mí abata kan nínú awan abata ọgbà idẹra wa níbẹ , pepele ìdúró sọrọ mí sì wà lórí adágún omi mi»[16]. [16] wan panupọ lórí rẹ Al-Bukhari, pẹlu onka (1195), àti Muslim, pẹlu onka (1390).

Kò si ọlá kan pàtó ti o wa nipa irun kiki ni Araodọh (abàtá), ṣùgbọ́n o ti fẹsẹmulẹ pé o jẹ abata kan ninu awọn abata Aljanna -gẹgẹ bi hadisi Bàbá ololongbo kékeré (Huraira,) -ki Ọlọhun yọnu si i- ti o ti ṣiwaju ṣe fihan-. Awọn iṣẹ́ ìjọsìn a sì máa lọlá sí pẹ̀lú ọlá àsìkò wọn àti ààyè wọn.

Olubẹwo yíò yan àwọn àsìkò tí ó bójú mu láti kirun ní Araodọh, yíò sì se ìtopinpin àwọn àsìkò tí àpéjọpọ̀ ( idifunfun) bá dínkù níbẹ̀. Kò gbọdọ̀ kó ìyọnu bá àwọn arákùnrin rẹ̀ musulumi, kò sì gbọdọ̀ gbé ẹsẹ̀ kọjá orí àwọn ènìyàn, bẹ́ẹ̀ ni kò gbọdọ̀ kọjá níwájú àwọn tí wọ́n ń kirun nítorí àti kirun níbẹ̀. Nítorí pé irun kíkí ní Araodọh jẹ́ irun àfikún, kò yẹ kí á fi iṣẹ́ èèwọ̀ wá ọ̀nà sí i. Bákan náà, ó yẹ kí olubẹwo se àkíyèsí àti pé kí ó tẹ̀lé àwọn ìlànà pàtó àti àwọn ètò tí a gbé kalẹ̀ fún wíwọ inú Araodọh, kí ó yan àwọn àsìkò tí ó bójú mu, kí ó sì fọwọ́sowọ́pọ̀ pẹ̀lú àwọn tí wọ́n ń darí wíwọlé àwọn olubẹwo síbẹ̀.

Lílo anfaani àwọn àsìkò pẹ̀lú pípọ̀ ní ṣíṣe àwọn iṣẹ́ rere èyí tí yóò sún-un mọ́ Ẹlẹ́dàá rẹ̀, Ẹni tí ọlá Rẹ̀ ga, bíi ìrun, àti kika Kuraani, àti ìrántí Ọlọhun, àti àdúà, àti wíwà ní àwọn àpéjọ ìrántí Ọlọhun, àti àwọn ìdánilẹ́kọ̀ọ́ ẹ̀sìn, àti àwọn ibùdó kíkọ́ Kuraani Alápọ̀nle, àti àwọn mìíràn bẹ́ẹ̀ bẹ́ẹ̀ lọ.

Bíbọ̀wọ̀ fun iwe Ọlọhun -ti agbara ati ọla Rẹ ga- àti dídáàbòbò ó kuro nibi fífi àwọn ìwé inú rẹ̀ ṣeré, àti kíkọ nnkan sí i lára, tabi yiyẹpẹrẹ rẹ àti gígàn án nípa fífi bàtà sí ẹ̀gbẹ́ rẹ, tabi fífi sí orí ilẹ̀ àti bẹẹbẹẹ lọ, fun ọrọ Rẹ -ti ọla Rẹ ga-: (Bẹẹ ni Ìyẹn se rí (nìyẹn). Ẹnikẹ́ni tí ó bá pàtàkì àwọn n̄ǹkan tí Allāhu fi ṣe àríṣàmì fún ẹ̀sìn ’Islām, dájúdájú ó wà lára níní ìbẹ̀rù Allāhu nínú ọkàn. [Suuratul Hajj: 32].

Rirẹ oju nilẹ kuro nibi nnkan ti Ọlọhun Alagbara, Ọlọla ṣe leewọ: O jẹ ọranyan lori olubẹwo Mọsalasi Anabi ki o rẹ oju rẹ nilẹ kuro nibi nnkan ti ko lẹtọ fun un lati wo, ki o si mọ titobi dida ẹṣẹ ni awọn ibùdó wọnyi, ati awọn ìyá tí yóò tara rẹ jáde , nítorípé àwọn iṣẹ́-ẹ̀ṣẹ̀ máa ń tóbi síi ní ìwọ̀n àti ní irú pẹ̀lú títóbi àsìkò àti aàyè, bẹ́ẹ̀ náà ni kí o se àwọn iṣẹ́ ìgbọràn àti itẹle aṣẹ Ọlọhun, ki obinrin Musulumi si fi ko ará rẹ pẹlu lílo aṣọ ibori àti ibo ará rẹ, gẹgẹ bí Hijab ti Sharia, lai ni fi ọṣọ han nitori ki o ma baa kò waala ba awọn ọkunrin, nitoripe ẹṣẹ eleyi tobi.

Ikilọ fún ní kuro nibi sí ṣe airoju pẹlu yiya aworan tabi wiwo àwọn aworan àti àwọn ègé fídíò ninu fóònù alágbèéká ṣiṣe , ọ̀ràn náà sì lewu síi bí àwọn aworan àti àwọn ègé fídíò wọ̀nyí bá jẹ́ èyí tí wọn se leewọ.

Pípa Mọṣalaasi Anọbi mọ́ kúrò níbi gbogbo ohun tí kò yẹ fún un, bíi jíjà, gbígbé ohùn sókè, kíkede ohun ìní tó sọnù, àti títàjà, àti irú àwọn nǹkan bẹ́ẹ̀ tí kò yẹ nínú rẹ̀ tàbí ní àwọn Mọṣalaasi yòókù; nítorí hadisi Bàbá ololongbo kékeré-kí Ọlọ́hun yọ́nú sí i- láti ọ̀dọ̀ Anọbi -kí ìkẹ́ Ọlọ́hun àti ọlá Rẹ̀ máa bá a- pé ó sọ wípé: «Tí ẹ bá rí ẹni tí ó n ta tàbí tí ó n rà nínú Mọsalasi, kí ẹ sọ pé: Kí Allāhu má fún òwò rẹ lérè, tí ẹ bá sì rí ẹni tí ó n kéde nnkan sísọnu nínú rẹ̀, kí ẹ sọ pé: Kí Allāhu má dá a padà fún ọ»[17]. [17] Tirmidhiy ni o mu jade, pẹlu ounka (1321), ati Ibnu Khuzaymah, pẹlu ounka (1305), pẹ̀lú isafiti tó ni àlàáfíà.

Ṣiṣe itara lori imọtoto ara ẹni, ati ṣiṣe iṣọra kuro ninu awọn oorun ti a korira gẹgẹbi alubọsa ayu ati alubọsa elewe ati oorun siga ati oogun, ati iru bẹẹ ninu ohun ti o maa nfa inira fun awọn ọmọ iya rẹ ti nkirun; nitori ẹgbawa Jaabir ọmọ Abdullaah – ki Ọlọhun yọnu si i – o sọ pe: dajudaju Ojiṣẹ Ọlọhun - kí ìkẹ́ Ọlọ́hun àti ọlá Rẹ̀ máa bá a - sọ pe: «Ẹnikẹni ti o ba jẹ alubọsa ayu tabi alubọsa elewe, ki o yaa yẹba fun wa - tabi o sọpe: ki o yẹba fun mosalasi wa - atipe ki o ya joko si ile rẹ»[18]. [18] Bukhōriy ni o gbe e jáde pẹlu ounka (7359), àti Musilim pẹlu ounka (564).

Ṣíṣe ojúkòkòrò lórí ìmọ́tótó masalasi Anọbi àti pé kí a má ṣe da ìdọ̀tí sílẹ̀ nínú mọsalasi àti ní àwọn àgbàlá rẹ̀, gẹ́gẹ́ bíi ajẹkù oúnjẹ àti àwọn ohun èlò ìsìnù, pàápàá jùlọ nínu oṣù Rọmọdọọn, tàbí títu itọ́ sílẹ̀ ní àwọn ọ̀nà àárín àti àwọn àgbàlá, àti bẹ́ẹ̀ bẹ́ẹ̀ lọ.

Yiyagò fún kiki irun nínú àwọn ọ̀nà àbùjá àti níbí ẹnu àwọn ilẹ̀kùn àti àwọn ibi tí èrò pọ̀ sí, nítorí àwọn ìbàjẹ́ tí ó máa n tìdí rẹ̀ yọ, àti dídí àwọn ọ̀nà mọ́, àti ṣíṣe ìpalára fún àwọn Musulumi.

Àwọn ọkùnrin àti àwọn obìnrin yóò máa kirun ní àwọn ààyè tí a yà sọ́tọ̀ fún olúkúlùkù wọn, nínú Mọsalasi Anabi tàbí ní àwọn gbàgede rẹ̀, ọkùnrin kò gbọdọ̀ kirun ní ẹ̀gbẹ́ obìnrin, bẹ́ẹ̀ ni obìnrin kò gbọdọ̀ kirun ní ẹ̀gbẹ́ ọkùnrin, pẹ̀lú ṣíṣọ́ra láti má ṣe ṣáájú Imāmù ni gbogbo ọnon tí yóò ba fí rọrun.

Fífi ẹsẹ òsì ṣáájú nígbà ìjáde kúrò ní mọsalasi, yóò sì sọ pé: «Allāhummọ innī as’aluKa min fadliKa»[19]، Tabi ki o se asalatu fun anabi - ki ikẹ ati ọla Ọlọhun maa ba a - yio si sọ pe: «Robbi igfir lī dhunūbī, waftah lī abwāba fadliKa» (Oluwa mi, forí àwọn ẹ̀ṣẹ̀ mi jìn mí, kí o sí ṣí àwọn ìlẹ̀kùn oore-ọ̀fẹ́ Rẹ fún mi)[20]. [19] Muslim ni o gbe e jade (713). [20] Tirmidhiy ni o mu jade, pẹlu ounka (314), pẹ̀lú ìranwọ́ tó péye.

Ẹlẹẹkẹrin ni: Awọn ìdájọ àti ẹkọ abẹwo sí saare Anabi (kí ikẹ Ọlọhun àti ọlá Rẹ máa ba a) àti saare àwọn ọrẹ Rẹ méjèèjì (kí Ọlọhun yọnu si awọn méjèèjì).

Ṣíṣe abẹwo sí saare Anabi, kí ikẹ Ọlọhun àti ọlá Rẹ máa ba a, àti saare àwọn ọrẹ rẹ méjèèjì: Abubakar àti Umar, kí Ọlọhun yọnu si wọn, jẹ́ ohun tí ó dára fún àwọn ará Mọdina àti fún ẹnikẹ́ni tí ó bá wá síbẹ̀ gẹ́gẹ́ bí àlejò àti olùṣe-abẹ̀wò; nítorí àwọn ẹ̀rí gbogboogbò tó fi hàn pé ṣíṣe abẹwo sí àwọn saare bá òfin mu, lára wọn ni ọ̀rọ̀ Anabi, kí ikẹ Ọlọhun àti ọlá Rẹ máa ba a, tó sọ pé: «Moti kọ fún yin láti ṣe abẹwo sí awàn saare, ni sìn ẹ se àbẹwò wọn»[21]. [21] Muslim ni o gbe e jade (977).

Dájú dájú Ẹ̀rí tó sì ń tọ́ka sí ọlá itọrẹ àlàáfíà fún Anabi - ki ikẹ ati ọla Ọlọhun maa ba a - lẹ́yìn ikú rẹ̀ ni ọ̀rọ Anabi - ki ikẹ ati ọla Ọlọhun maa ba a - tí ó sọ pé: «Ko si ẹnikankan ti yio salaamọ simi, ayaafi ki Ọlọhun Alagbara ati Ọlọla da ẹmi pada simi lara titi maa fi da a loun salamọ rẹ»[22]. [22] Ahmad ni o gbe e jáde, nínú tira Al-Musnad pẹlu ounka: (10815), pẹlu ise afiti tí o dára.

* Kò sí nínú òfin ẹṣin fún àwọn obìnrin láti ṣe àbẹwò sí saare rẹ̀ - ki ikẹ ati ọlá Ọlọhun maa ba a - tàbí saare ẹlòmíràn nínú àwọn Musulumi, nítorí pé dájúdájú bíbẹ àwọn saare wò jẹ́ ohun tí ó l'ẹtọọ fún àwọn ọkùnrin, ṣùgbọ́n àwọn obìnrin, a ti kọ̀ọ fún wọn láti máa ṣe àbẹwò sí àwọn saare, láti ọ̀dọ̀ ọmọ Abbas - kí Ọlọ́hun yọ́nú sí àwọn méjèèjì - ó sọ pé: «Ojiṣẹ Ọlọhun - ki ikẹ ati ọla Ọlọhun maa ba a - ti ṣẹbi le awọn ọbinrin ti wọn n ṣe abẹwo saare, ati awọn ti wọn n sọ wọn di Mọsalasi, ti wọn si n tan atupa si i»[23]، Láti ọdọ bàbá ololongbo kékeré - ki Ọlọhun yọnu si i-: «Dajudaju Anabi – ki ikẹ ati ọla Ọlọhun maa ba a – sẹbi le awọn olùṣe abẹwo saare lóbìnrin»[24]. [23] Abu Daa'ud ni o gbe e jade (3236), ati Tirmidhi (320), ati Nasa’i (2043). [24] Tirmidhiy ni o mu jade (1056), ati Ibnu Mājah (1576), pẹlu ẹgbawa to dara.

Kò sì lẹ́tọ̀ọ́ láti ṣe ìrìn-àjò láti lọ bẹ saare Anabi - ki ikẹ ati ọla Ọlọhun maa ba a - wò pé kí ó nínu pẹ̀lú ìrìn-àjò rẹ̀ pé òun fẹ́ lọ bẹ saare nìkan wò, ṣùgbọ́n kí ó nínu pẹ̀lú ìrìn-àjò rẹ̀ láti ṣe àbẹwò sí Mọ́sálásí àti láti kirun nínú rẹ̀, tí ó bá sì fìdí kalẹ̀ ní ìlú Mòdínà, a ṣe é ní òfin fún un láti bẹ saare wò, gẹ́gẹ́ bí a ti ṣe é ní òfin fún àwọn olùgbé Mòdínà nínú àwọn ará ibẹ̀; nítorí ọ̀rọ̀ Anabi - ki ikẹ ati ọla Ọlọhun maa ba a - tó sọ pé: «A kò gbọdọ̀ rin irin ajo ayaafi lọ si awọn mọsalasi mẹta: mọsalasi mi yii, Mọsalasi Harami, ati Mọsalasi Al-Aqsa»[25]. [25] Bukhōriy ni o gbe e jáde, pẹlu ounka: (1189), àti Muslim, pẹlu ounka: (1397), gbólóhùn náà ti Muslim ni.

Àwọn ẹ̀kọ́ tí ó bá òfin mú nípa ṣíṣe abẹwo sí saare Anabi (kí ikẹ àti ọlá Ọlọ́hun máa bá a), àti saare àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀ méjèèjì (kí Ọlọ́hun yọ́nú sí wọn).

Olùṣe-abẹwo yóò dúró ní iwájú saare Anabi (kí ikẹ ati ọla Ọlọhun máa bá a) ní ìkọjú sí i, yóò sì salamọ sí Anabi (kí ikẹ ati ọla Ọlọhun máa bá a) pẹlu ẹ̀kọ́ àti rírẹ ohun silẹ, ní ẹni tí yóò sọ pé: (Àlàáfíà kí o máa bá ọ, ìwọ ojisẹ Ọlọhun, àti ìkẹ́ Ọlọhun àti ìbùkún Rẹ̀), tí ó bá sì fi kún ìyẹn, tí ó wá sọ pé: (mo jẹri pé o ti jisẹ náà dé òpin, o sì ti ṣe asepe ìgbà fipamọ, o si se ìkìlọ mimọ fún àwọn ìjọ rẹ, o sì ti jagun sí ojú ònà Ọlọhun ní tòótọ) kò sí aburú níbẹ̀; nítorí pé gbogbo èyí òótọ́ ni.

Lẹ́yìn náà yóò gbé ìgbésẹ̀ kan sí apá ọ̀tún rẹ̀ kí ó lè kọjú sí saare Àbubakir olódodo kí Ọlọhun yọnu sí, yóò wá sọ pé: (Àlàáfíà Ọlọhun kí o má bà ọ irẹ Abi Bakiri olódodo, Àlàáfíà Ọlọhun kí o má bà ọ irẹ Arọ́pò òjíṣẹ Ọlọhun kí ikẹ Ọlọhun àti ọlá Rẹ máa ba, kí Ọlọhun yọnu sí ọ kí O sì tẹ́ ọ lọ́rùn, kí Ọlọhun sì san ọ́ ní ẹsan rere fún àwọn ìjọ Muhammad kí ikẹ Ọlọhun àti ọlá Rẹ máa ba).

Lẹyìn náà yóò gbé ìgbésẹ̀ kan sí apá òtún rẹ̀ láti wà ní iwájú saare Umar ọmọ Khattob kí Ọlọhun yọnu sí, yóò sọ pé: (Àlàáfíà Ọlọhun kò má bà ọ irẹ Umar Al-Farooq, kí Ọlọhun yọnu sí ọ kí ó sì jẹ́ kí inú rẹ dùn, kí Ó sì san ọ́ ní esan rere ní ipò ìjọ Muhammad kí ikẹ Ọlọhun àti ọlá Rẹ máa ba a).

ọmọ Umar - ki Ọlọhun yọnu si awọn mejeeji - máa ń wá sí saare Anabi - ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a - tí o bá ti dé láti ìrìn-àjò, ni yoo wa sọ pé: «Àlàáfíà kí ó máa bá ọ, ìwọ Òjíṣẹ́ Ọlọhun, Àlàáfíà kí ó máa bá ọ, ìwọ Abū Bakr, Àlàáfíà kí ó máa bá ọ, ìwọ bàbá mi, lẹ́yìn náà yóò pẹyinda »[26]. [26] Al- Bayhaki lo gbe e jáde nínú tira As-sunanil Kubrah (10271), pẹ̀lú ìsafiti tí ó ní àlàáfíà.

Kò gbọdọ fọwọ kan ogirì sàréè tàbí agọ rẹ̀, kò sì gbọdọ fẹnu kan wọ́n:

Imām Mālik - ki Ọlọhun kẹ ẹ - sọ pe: Tí ó bá fẹ́ salamọ sí Anabi -kí ikẹ ati ọla Ọlọhun máa bá a-, yóò dúró tí ojú rẹ̀ yóò dojú kọ saare; kì í ṣe sí Al-kibla ( ibudajukọ) , yóò súnmọ́ ọn, yóò sì salamọ, kò sì ní í fi ọwọ́ kan saare náà" [27]. [27] Ash-Shifā tii se tira tí il-Qāḍī ‘Iyāḍ se (2/199).

Àti pé àwọn Imọmu asiwaju ẹsin tí panupọ, wọ́n si ṣọ̀kan lórí pé kí a má fi ọwọ́ kan saare Anabi – ki ikẹ ati ọla Ọlọhun maa ba a –, kí a sì má ṣe fẹnu kò ó.

Ko ní dúró pẹ́ níbẹ̀ saare, yóò salamọ, lẹ́yìn náà yóò sì pẹyìndà.

Imam Mālik - ki Ọlọhun kẹ ẹ - sọ pe: "Mi ò rí i pé kí èèyàn dúró níbi saare Anabi - kí ikẹ àti ọlá Ọlọ́hun máa bá a - láti ṣe àdúrà, ṣùgbọ́n kí ó kí pẹlu sàlámon , kí ó sì máa lọ" [28]. [28] Ash-Shifā ti Qāḍī 'Iyāḍ (2/ 199).

Naafi' - ki Ọlọhun ba wa ṣe ikẹ Rẹ fun un- naa sọ pe: "Ọmọ Umar a máa ń salamọ níbi saare.. mo rí i nígbà ọgọ́rùn-ún àti jù bẹ́ẹ̀ lọ tí ó máa ń wá sí bí saare, tí yóò sì sọ pé: “Àlàáfíà kí ó máa bá Anabi - kí ikẹ Ọlọhun àti ọlá Rẹ máa bá a. Àlàáfíà kí ó máa bá Abi Bakiri, Àlàáfíà kí ó máa bá bàbá mi,” lẹyìn náà yóò sí pẹyinda " [29]. [29] Al-Ājurriy ni o gbe e jáde nínu ìwé Ash-Sharī'ah (5/2374), pẹlu onka (1853).

Ṣugbọn èyí tí awan apakan olubẹwo nṣe bí gbígbé òunh sókè níbi saare rẹ - kí ikẹ Ọlọhun àti ọlá Rẹ máa ba a - àti diduro pẹ níbẹ òun ni o yatosi òun tí wan se ni ilana ẹṣin.

Kò lẹ́tọ̀ láti pe Òjíṣẹ́ kí ikẹ Ọlọhun àti ọlá Rẹ̀ má bà, tàbí ẹlòmíràn nínú àwọn ẹ̀dá fún mímú ànfàní wá tàbí dída ìpalára sẹ́hìn, tàbí wíwa ìbiya búkàátà, tàbí ìdásílẹ̀ kúrò nínú wàhálà, tàbí ìwòsàn aláìsàn, tàbí wíwa ìpẹ̀bẹ̀, tàbí ìgbàlà kúrò nínú ìyà, tàbí irú bẹ́ẹ̀ nínú àwọn àdúà; nítorí pé pipe ẹni tí ó yàtọ̀ sí Ọlọhun nípa ohun tí ẹnikẹ́ni kò ní agbára lé lórí àyàfi Ọlọhun jẹ́ èèwọ̀ àti ṣirik ṣíṣe ẹbọ ńlá, Ọlọhun ti ọlá Rẹ̀ ga sọ pé: « Atipe Olúwa yín sọ pé: “Ẹ pè Mí, kí N̄g jẹ́pè yín. Dájúdájú àwọn tó ń ṣègbéraga nípa jíjọ́sìn fún Mi tàbí pípé Mí , wọn yóò wọ inú iná Jahanamọ ní ẹni yẹpẹrẹ.” [Gaafir: 60], Ọba- ti mimọ n bẹ fun Un- sọ pe: Dájúdájú àwọn tí ẹ̀ ń pè lẹ́yìn Allāhu, ẹrú bí irú yin ni wọ́n. Nítorí náà, ẹ pè wọ́n wò, kí wọ́n da yín lóhùn tí ẹ bá jẹ́ olódodo. [Al-A'raaf:194], Ọba tí Ó gbòǹgbòn ní ipò gíga Rẹ̀ sọ pé: « Ati pé Dájúdájú àwọn mọ́sálásí ń jẹ́ ti Allāhu. Nítorí náà, ẹ kò gbọ́dọ̀ pe ẹnì kan pẹ̀lú Allāhu» [Sūrah Al-Jinni: āyah 18].

A kò gbọdọ̀ kepe Ọlọ́hun níbi saare; bí ènìyàn bá fẹ́ ṣe àdúà, kí ó sún síwájú kúrò níbi saare, kí ó kọjú sí Qiblah, kí ó sì ṣe àdúà. Kò sì gbọdọ̀ kọjú sí saare nígbà tí ó bá ń ṣe àdúrà lọwọ.

Imam Malik -ki Ọlọhun kẹ ẹ- ti sọ pe: Mi ò rí i pé kí ènìyàn dúró níbí saare Anabi - ki ikẹ ati ọla Ọlọhun maa ba a - kí ó máa ṣe àdúà.

Kò sí nínú òfin ẹṣin láti máa lọ sí saare léraléra nígbà tí a bá wọ mọsalasi tàbí tí a bá jáde kúrò níbẹ̀, kìí ṣe fún àwọn ará ìlú Mẹdina bẹ́ẹ̀ni kìí ṣe fún àwọn olùṣàbẹ̀wò láti ìta rẹ̀, nítorí a bẹ̀rù pé kí èyí má di sísọ saare di ibi ààyè ṣíṣe ọdún.

"Ati pe Ojiṣẹ Ọlọhun - ki ikẹ ati ọla Ọlọhun maa ba a - ti kọ fún wa kuro nibẹ nitori naa ni o fi sọ pe:" «Ẹ má ṣe sọ saare mi di àáye àjọ̀dún, ẹ sì má ṣe sọ ilé yín di saare, níbikíbi tí ẹ bá wà, ẹ maa ṣe asalatu ( e máa tọrọ ikẹ fún mi ) fún mi; dájúdájú asalatu yín yóò máa dé ọ̀dọ̀ mi»[30]. [30] Ahmad lo gbe e jáde nínú tira Musnad rẹ, pẹlu ounka (8804), pẹlu isafiti ti o dáa.

Itumọ ọrọ “ẹ ma sọ saare mi di ọdun” ni pípadà lọ síbẹ̀ léraléra ní àsìkò kan tàbí ní ipò kan pàtó, gẹ́gẹ́ bíi sísọ àbẹ̀wò rẹ̀ di pàtó lojoojúmọ́, tàbí lọ́sọ̀ọ̀sẹ̀, tàbí loṣooṣù. Tàbí ní àwọn ipò kan pàtó tí a fi máa ń ṣe àbẹ̀wò sí i nígbà tí wọ́n bá wáyé, a sì tún sọ pé: ìyẹn ni pé kí ẹ má ṣe sọ ọ́ di àsìkò àpéjọ tí ẹ óò máa kóra yín jọ síbẹ̀. [31]Wo: Al-Mufradaat ti Ar-Rogibu Al-Asfahaani (ojú ìwé: 594) Àlàyé inú ọkàn nípa ṣíṣe gbigbe àwọn saare ga leewọ ti Ash-Shawkaani (ojú ìwé:16).

Imamu Mālik - ki Ọlọhun kẹ ẹ - si sọ pe: ""Ko jẹ dandan fun ẹni ti o ba wọ Mọṣalaṣi ti o si jade ninu rẹ ninu awọn ara ilu Mẹdinah lati duro níbi saare, ṣugbọn fun awọn alejo ni eyi jẹ"[32]." [32] Ash-Shifā' li'l-Qāḍī 'Iyāḍ (2/ 204), Al-Madkhal li-Ibnil Hājj (1/ 262).

Ati ọrọ rẹ, kí Ọlọhun ṣe ìkẹ fún un: "Wípé èyí jẹ́ fún àwọn àlejò nìkan": ìyẹn ni wípé àbẹwò ní gbogboogbò, kìí ṣe ìpaara àbẹwò nígbà wiwọlé àti jíjáde.

Kò tọ́ láti dúró síwájú saare bí irisi ẹni tí nkirun nípa gbígbé ọwọ́ kan lé èkejì lórí igbáàyà tàbí ní abẹ́ rẹ̀; nítorí pé irisi yìí jẹ́ fún irun kiki nìkan, ó sì jẹ́ irisi iyẹpere àti ìtẹríba tí kò yẹ fún ẹnikẹ́ni àfi fún Ọlọhun Ọba tó ga jùlọ.

A kì í kọjú sí saare láti ibi jíjìn láti fi salamọ sí Anabi -kí ikẹ Ọlọhun àti ọlá Rẹ má bà- gẹ́gẹ́ bí àwọn kan nínú àwọn ènìyàn ṣe máa ń ṣe; nítorí pé èyí kìí ṣe ohun tí àwọn Saabe -kí iyọnu Ọlọhun maa ba wọn- máa ń ṣe, bẹ́ẹ̀ ni kìí ṣe ohun tí àwọn enisiwaju enire máa ń ṣe nínú àwọn Imọ́ọ̀mù mẹ́rẹ̀ẹ̀rin àti àwọn mìíràn yàtọ̀ sí wọn.

AKò gbọdọ kọjú sí saare alápọnle náà pẹ̀lú ṣíṣe ádúrà tàbí kíka al-kurani àti irú nkán tí o ba jẹ mọn irú rẹ̀ láti apá ibikíbi, nítorí èyí jẹ́ ọ̀kan nínú àwọn adadaalẹ tí ó ti ṣáájú. Kò sì tọ́ fún Musulumi láti ṣe adadaalẹ nínú ẹ̀sìn rẹ̀ ohun tí Ọlọ́hun kò yọ̀ǹda. Dájúdájú Imam Malik - kí Ọlọ́hun kẹ́ ẹ - ti kọ àwọn iṣẹ́ tó jọ èyí, ó sì sọ pé: "Kò sí ohun tí yóò tún ìgbẹ̀yìn ìjọ yíì ṣe bí kò ṣe ohun tí ó tún ti àwọn ẹni àkọ́kọ́ rẹ̀ ṣe"[33]. [33] Majmuu'u Fataawaa ti Ibnu Baaz (16/110).

Aiko se airoju pẹlu yiya aworan ati ìgbóhùnsáfẹ́fẹ́ lẹsẹkẹsẹ láarin asìkò ikíni sí Anabi - ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a -.

Ki ikẹ ati ọla Ọlọhun maa ba Anabi wa Muhammad, ati awọn arale rẹ ati awọn saabe rẹ, kí ọlà si maa bá wọn.