الأذكار التي تقال صباحًا ومساءً

الأذكار التي تقال صباحًا ومساءً

الأذكار التي تقال صباحًا ومساءً كتبها بخط يده فضيلة الشيخ العلامة محمد بن صالح العثيمين من صحيح الأذكار الثابتة عن النبي -صلى الله عليه وسلم-

Language: lang_yo
Prepared by:
Version: 2.0
Translations 56
Amharic Assamese Azerbaijani Bengali +52
Attachments 7
PDF
Audio
Video
+3

Pelu oruko Olohun Oba Ajoke aye Oba Asake orun. Àwọn asikiri ti a maa n sọ ni aarọ ati irọlẹ

Allāhu, kò sí ọlọ́hun kan tí ìjọ́sìn tọ́ sí àfi Òun, Alààyè, Alámòjúútó-ẹ̀dá. Òògbé kì í ta Á. Àti pé oorun kì í kùn Ún. TiRẹ̀ ni ohunkóhun t’ó wà nínú àwọn sánmọ̀ àti ohunkóhun t’ó wà nínú ilẹ̀. Ta ni ẹni tí ó máa ṣìpẹ̀ lọ́dọ̀ Rẹ̀ àfi pẹ̀lú ìyọ̀ǹda Rẹ̀? Ó mọ ohun tí ń bẹ níwájú wọn àti ohun tí ń bẹ lẹ́yìn wọn. Wọn kò sì ní ìmọ̀ àmọ̀tán nípa kiní kan nínú ìmọ̀ Rẹ̀ àfi ohun tí Ó bá fẹ́ (fi mọ̀ wọ́n). Àga Rẹ̀ gbààyè ju àwọn sánmọ̀ àti ilẹ̀. Ṣíṣọ́ sánmọ̀ àti ilẹ̀ kò sì dá A lágara. Allāhu ga, Ó tóbi. Aayah Kursiyyu: 255, Bakọra

Òjíṣẹ́ náà (sollalāhu 'alayhi wa sallam) gbàgbọ́ nínú ohun tí wọ́n sọ̀kalẹ̀ fún un láti ọ̀dọ̀ Olúwa rẹ̀. Àwọn onígbàgbọ́ òdodo náà (gbàgbọ́ nínú rẹ̀). Ẹnì kọ̀ọ̀kan (wọn) gbàgbọ́ nínú Allāhu, àwọn mọlāika Rẹ̀, àwọn Tírà Rẹ̀ àti àwọn Òjíṣẹ́ Rẹ̀. A kò ya ẹnì kan sọ́tọ̀ nínú àwọn Òjíṣẹ́ Rẹ̀. Wọ́n sì sọ pé: “A gbọ́ (àṣẹ), a sì tẹ̀lé (àṣẹ). À ń tọrọ àforíjìn Rẹ, Olúwa wa. Ọ̀dọ̀ Rẹ sì ni àbọ̀ ẹ̀dá.” Allāhu kò làbọ ẹ̀mí kan lọ́rùn àfi ìwọ̀n agbára rẹ̀. (Ẹ̀san) ohun tí ó ṣe níṣẹ́ (rere) ń bẹ fún un. (Ìyà) ohun tí ó ṣe ní’ṣẹ́ (ibi) ń bẹ fún un pẹ̀lú. Olúwa wa, má ṣe mú wa tí a bá gbàgbéra tàbí (tí) a bá ṣàṣìṣe. Olúwa wa, má ṣe di ẹrù t’ó wúwo lé wa lórí, gẹ́gẹ́ bí O ṣe dì í ru àwọn t’ó ṣíwájú wa. Olúwa wa, má ṣe dìrù wá ohun tí kò sí agbára rẹ̀ fún wa. Ṣàmójú kúrò fún wa, foríjìn wá, kí O sì ṣàánú wa. Ìwọ ni Aláfẹ̀yìntì wa. Nítorí náà, ràn wá lọ́wọ́ lórí ìjọ aláìgbàgbọ́. Aayah 285 – 286, Bakọra

(Sọ pé: "Òun ni Allāhu, Ọ̀kan ṣoṣo) (Sọ pé: "Mo sá di Olúwa òwúrọ̀ kùtùkùtù) (Sọ pé: Mo sá di Olúwa àwọn ènìyàn). A o ka àwọn Surah naa ní pípé ni ẹẹmẹta.

Mo wá iṣọra pẹ̀lú àwọn ọ̀rọ̀ Ọlọ́hun tó pé kúrò níbi aburu ohun tí O dá. (A o sọ ọ ni ẹẹmẹta).

Ní orúkọ Ọlọ́hun, Ẹni ti O ṣe pé, pẹ̀lu orúkọ Rẹ̀, kò si nkan kan ti o le kó ìnira báni, ní ilẹ ati sanmọ, Òun sì ni Olùgbọ́, Onímímọ̀. (A o sọ ọ ni ẹẹmẹta).

Mo yọ́nú sí Ọlọ́hun ní Olúwa mi, Mo yọ́nú sí Islam ní ẹ̀sìn mi, Mo sì yọ́nú sí Muhammad – kí ikẹ ati ọla Ọlọ́hun maa ba a – ní Anabi mi. (A o sọ ọ ni ẹẹmẹta).

A di òwúrọ̀, ti Ọlọhun si ni ijọba ní òwúrọ̀ naa, ọpẹ ni fún Ọlọhun, kò sí ọlọhun miran ayafi Ọlọhun (Allahu) nikan ṣoṣo, Ko si orogún fun Un, tiRẹ̀ ni ijọba, tiRẹ̀ sì ni ẹyìn, Oun ni Alagbara lori gbogbo nkan, Ìrẹ Ọlọhun mi, mo n beere lọwọ Rẹ oore nkan ti o wa ní ọjọ oni ati oore nkan ti o wa lẹyin ọjọ oni, mo si n wa iṣọ pẹlu Rẹ kuro nibi aburu nkan ti o wa ni ọjọ oni ati aburu nkan ti o wa lẹyin ọjọ oni, Irẹ Ọlọhun mi, mo n wa Ọ ni Olùṣọ́ kuro nibi òròjú, ogbó ati ìdàgbà burúkú, mo si n wa Ọ ni Olùṣọ́ kuro nibi iya ina ati iya inu saare. Ní àṣálẹ́, o maa sọ pe: A di aṣalẹ, ti Ọlọhun si ni ijọba ni aṣalẹ naa, O maa tún sọ pe: Irẹ Ọlọhun mi, mo n beere lọwọ Rẹ oore nkan ti o wa ni alẹ́ yii … A o sọ ọ títí dé ìparí, a o wí pé (A di aṣalẹ, ti Ọlọhun si ni ijọba ni aṣalẹ naa) dipo (A di òwúrọ̀, ti Ọlọhun si ni ijọba ní òwúrọ̀ naa), a o sì wipe: (alẹ́ yii) dipo (ọjọ yii).

Irẹ Ọlọ́hun, Ìwọ ni O mu wa di owurọ, Iwọ ni O mu wa di aṣalẹ, Iwọ ni O n mú wa yè, Iwọ ni O n mu wa kú, Ọ̀dọ̀ Rẹ sì ni àjíǹde ẹ̀dá wà. Ní àṣálẹ́, o maa sọ pe: Irẹ Ọlọhun, Iwọ ni O mu wa di aṣalẹ, Iwọ ni O mu wa di owurọ, Iwọ ni O n mu wa kú, Iwọ ni O n mu wa yè, ọdọ Rẹ sì ni àbọ̀ ẹ̀dá

Irẹ Ọlọhun, ìdẹ̀ra yòówù kó bá mi di owurọ tabi ọkan ninu awọn ẹda Rẹ, lati ọdọ Rẹ nikan ṣoṣo ni o ti wá, ko si orogun fun Ọ, nitori naa, tiRẹ ni ẹyin, tiRẹ sì ni ọpẹ. Ní àṣálẹ́, o maa sọ pe: Ìdẹ̀ra yòówù kó bá mi di aṣalẹ.

(A o sọ ọ ni ẹẹmẹta),

Irẹ Ọlọhun, dájúdájú mo n tọrọ alaafia lọwọ Rẹ ní aye ati ọrun, Irẹ Ọlọhun, dajudaju mo n tọrọ àmójúkúrò ati alaafia lọwọ Rẹ ninu ẹsin mi, ayé mi, ará ilé mi, ati dukia mi, Irẹ Ọlọhun, bo aṣiri àwọn ìhòhò mi, fi mí lọkan balẹ nibi gbogbo ohun tí n bami lẹru, Irẹ Ọlọhun, ṣọ mi lati iwaju mi, lati ẹyin mi, lati apa ọtun mi, lati apa osi mi, àti láti apa oke mi, mo sì n wá ìsọ́ pẹlu títóbi Rẹ kuro nibi kí wọ́n fi àdánwò kàn mí lati isalẹ mi.

Irẹ Ọlọ́hun, Ìwọ ni Oluwa mi, ko si Ọlọhun miran ayafi Ìwọ, Ìwọ ni O dá mi, ẹru rẹ sì ni mo jẹ́, mo duro pẹlu majẹmu ati adehun Rẹ bí mo ti lagbara mọ, mo n wa ìṣọ́ lọdọ Rẹ kuro nibi aburu ohun tí mo ṣe níṣẹ́, mo jẹwọ idẹra Rẹ lori mi fun Ọ, mo sì jẹwọ ẹṣẹ mi, nítorí náà fori jin mi, nitori pé dajudaju kò sí ẹniti ó le fori jin eniyan ayafi Ìwọ.

Irẹ Ọlọ́hun, Oluṣẹda àwọn sanmọ ati ilẹ, Olumọ kọ̀kọ̀ ati gbangba, Oluwa gbogbo nkan ati Olukapa rẹ, mo n jẹrii pe ko si ọlọhun miran ayafi Ìwọ, mo n wa ìṣọ lọdọ Rẹ kuro nibi aburu ẹmi mi ati aburu eṣu ati ẹbọ tó n pèpè si, ati pé ki n ṣe aburu sí ẹmi ara mi tabi pé ki n ṣé e sí musulumi kan.

Irẹ Ọlọ́hun, mo jí ni owurọ ni ẹni tí n fi Ọ ṣe Ẹlẹ́rìí, mo sì n fi àwọn tó gbé aga alaaraṣi Rẹ dání ṣe ẹlẹ́rìí, ati àwọn Malaika Rẹ, ati àwọn Anabi Rẹ, ati gbogbo ẹda Rẹ, pé dajudaju Ìwọ ni Ọlọhun, ko si ọlọhun miran ayafi Ìwọ, àti pé dajudaju Muhammad ẹru Rẹ ni, ojiṣẹ Rẹ sì ni. Ní àṣálẹ́ Irẹ Ọlọ́hun, mo di àṣálẹ́ ... A o sọ ọ títí dé ìparí (ni ẹẹmẹrin)

Ko si ọlọhun miran ti ìjọsìn tọ si pẹ̀lú ẹ̀tọ́ ayafi Ọlọhun (Allah) nikan ṣoṣo, ko si orugun fun Un, tiRẹ ni ijọba, tiRẹ sì ni ẹyin, Ohun ni Alagbara lori gbogbo nkan. (A o sọ ọ nigba ọgọ́rùn-ún) ní òwúrọ̀ tabi àṣálẹ́.

Ọlọhun tó fún mi, ko si ọlọhun miran ti ìjọsìn tọ́ sí pẹ̀lú ẹ̀tọ́ ayafi Oun, Oun ni mo gbarale, Oun sì ni Ọba ti O ni aga aliaraṣi ńlá. (A o sọ ọ ni ẹẹmeje).

Mímọ́ ni fún Ọlọhun pẹlu ẹyìn ni fun Un (A o sọ ọ nigba ọgọ́rùn-ún) ni owurọ tabi àṣálẹ́. Tabi ni igba mejeeji.

Mo n tọrọ aforijin lọdọ Ọlọhun, Mo sì n ronupiwada lọ sí ọdọ Rẹ̀. (A o sọ ọ nigba ọgọ́rùn-ún).

Eyi ni ohun tí ó rọrùn lati kọ, Mo n beere lọwọ Ọlọhun Ọba Aleke ọlá pé kí Ó fi ṣe anfaani fún àwọn eniyan.

Muhammad Al-Salih Al-Uthaimeen ni o kọ ọ ní ọjọ 20-1-1418 AH.