رسالتان موجزتان في الزكاة والصيام

رسالتان موجزتان في الزكاة والصيام

Àwọn àkọsílẹ̀ ṣókí méjì lórí Zakah àti Ààwẹ̀.

Language: lang_yo
Prepared by: Abdul Azeez ọmọ Abdullah ọmọ Bāz
Version: 2.0
Translations 43
Assamese Azerbaijani Bengali Bosnian +39
Attachments 7
PDF
Audio
Video
+3

Àwọn àkọsílẹ̀ ṣókí méjì lórí Zakah àti Ààwẹ̀.

Ti Alfa àgbà Shaikh.

Abdul Azeez ọmọ Abdullah ọmọ Bāz

Kí Ọlọhun ba wa kẹ ẹ.

Iṣẹ́- ìwé àkọ́kọ́

Nípa Àwọn ìwádìí pàtàkì lórí Zakah

Ní orúkọ Allāhu, Àjọkẹ́-ayé, Àṣàkẹ́-ọ̀run.

Ọpẹ ni fun Ọlọhun nikan, ikẹ ati ọla ki o lọ maa ba ẹniti ko si Anọbi kankan mọ lẹyin rẹ, ati lori awọn ara ile rẹ ati awọn saabe rẹ, lẹyin naa:

Dájúdájú ohun tí ó mú ni kọ ọ̀rọ̀ yíì ni ìgbani-ní-ìyànjú àti ìránni-létí nípa ọ̀ranyàn Zakah, èyí tí ọ̀pọ̀lọpọ̀ nínú àwọn Musulumi ti fi ọwọ́ yẹpẹrẹ mú tí wọn kò sì yọọ́ jáde ní ìbámu pẹ̀lú ọ̀nà tí a pa láṣẹ, pẹ̀lú bí ọ̀rọ̀ rẹ̀ ṣe tóbi tó, àti jíjẹ́ ọ̀kan nínú àwọn orígun Islām márùn-ún èyí tí ilé rẹ̀ kò leè dúró dáadáa bí kò ṣe lórí wọn; nítorí ọ̀rọ̀ Ànábì - ki ikẹ ati ọla Ọlọhun maa ba a -: tí o sọ pé: «Wọ́n mọ Islaam pa lórí nǹkan márùn-ún: ìjẹ́rìí pé kò sí ẹni tí ìjọsìn ododo tọ́ sí àyàfi Allāhu, àti pé dájúdájú Muhammad òjíṣẹ́ Ọlọ́run ni, àti gbígbé irun dúró, àti yíyọ Zakah, àti gbígba ààwẹ̀ Ramadān, àti ṣíṣe Hajj sí Ilé Ọlọ́run»[1], Imam Bukhari ati Muslim lo gba a wa tí wọn si panupọ lórí lilalaafia rẹ. [1] Bukhari ni o gbe e jade pẹlu ounka (8), àti Muslim pẹlu ounka (16).

Ṣíṣe Sakah ni ọranyan lórí àwọn Musulumi jẹ́ ọ̀kan nínú àwọn ohun rere ẹ̀sìn Isilaamu tí ó hàn jùlọ, àti àbojútó rẹ̀ fún àwọn ọ̀rọ̀ àwọn olùgbàgbọ́ rẹ̀; nítorí pípọ àwọn ànfàní rẹ̀, àti ìbùkátà púpọ̀ tí àwọn aláìní Musulumi ní sí i.

Nínú àwọn ànfàní rẹ̀: fífi àwọn asopọ ìfẹ́ rinlẹ laarin àwọn ọlọrọ àti àwọn talika; nítorí pé a dá àwọn ẹ̀mí mọ́ ìfẹ́ ẹni tí ó ṣe dáadáa sí wọn.

Ninu rẹ ni: Fifọ ẹmi mọ ati ìsọdimímọ́ rẹ, ati gbigbe e jina si iwa aun k'okogun ati aun aniju, gẹgẹ bi Al-Qur'aani Alapọn-ọle ṣe tọka si itumọ yii ninu ọrọ Rẹ ti ọla Rẹ ga sọ pe: (Gba ọrẹ (Zakāh) nínú dúkìá wọn, kí o fi sọ wọ́n di ẹni mímọ́, kí o sì fi ṣe àfọ̀mọ́ fún wọn .. [At-Taobah: 103].

Nínú rẹ̀ ni: mímu Muslimi mọ ìwà ọrẹ-tita àti ṣíṣe aanu fún ẹni tí ó ní bukaata.

Ninu rẹ pẹlu ni: fifa àlùbáríkà ( ìbùkún) wá àti àlékún àti arọpo láti ọdọ Ọlọhun, gẹgẹ bi Ọlọhun ti ọla Rẹ ga ṣe sọ pe: ( ...àti pé ohunkóhun tí ẹ bá ná, Òun l’Ó máa fi (òmíràn) rọ́pò rẹ̀. Óhun sì ni O l’óore jùlọ nínú àwọn olùpèsè);. [Suratu Sabai: 39], ati ọrọ Anabi - kí ikẹ ati ọla Ọlọhun máa bá a - ninu hadīth ti o ni alaafia ni: Ọlọhun n sọ pe: «Irẹ Ọmọ Anọbi Adam nawo, Emi Yóò maa fi òmíràn rọ́pò...»[2]، Ati ohun ti o yatọ si ìyẹn nínú àwọn ànfàaní tí o pọ. [2] Muslim ni o gbe e jade (993).

Ìkìlọ̀ líle àti ileri ìyà sì ti wá lórí ẹni tí ó bá ṣahun rẹ̀ tàbí tí ó bá ṣe àìpé nípa yíyọ rẹ̀ jáde, Ọlọhun- ti ọla Rẹ ga- sọ pe: (... Àwọn tó sì ń kó wúrà àti fàdákà jọ, tí wọn kò sì máa ná an sí ojú-ọ̀nà Allāhu, fún wọn ní ìró ìyà ẹlẹ́ta-eléro), «Ní ọjọ́ tí A óò máa yọ́ (wúrà àti fàdákà náà) nínú iná Jahanamọ, A ó sì máa fi jó iwájú wọn, ẹ̀gbẹ́ wọn àti ẹ̀yìn wọn. (A sì máa sọ pé): “Èyí ni ohun tí ẹ kó jọ fún ẹ̀mí ara yín. Nítorí náà, ẹ tọ́ ohun tí ẹ kó jọ wò.» [Surah At-Tawbah: 34-35], Gbogbo dúkìá tí a kò yọ Sakat rẹ̀, ohun ni apẹpẹ ọrọ tí wọn yóò fii fí iya jẹ ẹni tí o nii ní Ọjọ́ igbende, gẹ́gẹ́ bí hadith toni àlàáfíà ṣe tọ́ka sí i láti ọ̀dọ̀ Ànábì - kí ikẹ ati ọla Ọlọhun máa bá a - pé ó sọ pé: «Kò sí oní wúrà tàbí fàdákà kan tí kò san ẹ̀tọ́ rẹ̀; bí kò ṣe pé ní Ọjọ́ igbende, wọn yóò sọ wọ́n di àwọn pẹlẹbẹ iná fún un; wọn yóò sì máa yọ́ ọ nínú iná Jahanamọ, tí wọn yóò máa fi jó ẹ̀gbẹ́ rẹ̀, iwájú rẹ̀, àti ẹ̀yìn rẹ̀. Nígbàkúgbà tí ó bá tutu, wọn yóò tún dá a padà fún un, ní ọjọ́ kan tí ìwọ̀n rẹ̀ jẹ́ àádọ́ta ẹgbẹ̀rún ọdún, títí tí A ó fi ṣe ìdájọ́ láàárín àwọn ẹrúsìn, tí yóò fi rí ipò rẹ̀: yálà sí inú Alùjànná ni, tàbí sí inú iná»[3]. [3] Muslim ni o gbe e jade (987).

Lẹ́yìn náà ni Anabi- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- dárúkọ oní rakunmi, mààlúù, àti àgùntàn tí kò yọ saka wọn, ó sì sọ pé a ó fi wọ́n jẹ ẹ́ níyà ni Ọjọ́ igbende .

O ni àlàáfíà lati ọdọ Ojiṣẹ Ọlọhun - ki ikẹ ati ọla Ọlọhun maa ba a - pe o sọ pe: “Ẹnikẹ́ni tí Allāhu bá fún ní ọrọ̀, tí kò sì yọ Sakāh rẹ̀, a ó sọ ọrọ̀ rẹ̀ di ejò olóró pápá kan fún un t’ó ní àmì dúdú méjì lójú rẹ̀, yoò dì í mọ́ ọn lọ́rùn ní Ọjọ́ igbende. Lẹ́yìn náà, yoò gbà á mú ní parikẹ́ rẹ̀ méjèèjì (ìyẹn, ẹ̀gbẹ́ ẹnu rẹ̀), lẹ́yìn náà, yoò sọ pé: ‘Èmi ni ọrọ̀ rẹ, èmi ni ìṣúra rẹ.’” Lẹ́yìn náà, Ànábì (kí ìkẹ́ àti ọlà Allāhu máa bá a) ka ọ̀rọ̀ Allāhu - Alápọnle - pé:(Kí àwọn t’ó ń ṣahun pẹ̀lú ohun tí Allāhu fún wọn nínú oore-àjùlọ Rẹ̀ má ṣe lérò pé oore ni fún wọn. Rárá, aburú ni fún wọn. A ó fí ohun tí wọ́n fi ṣahun dì wọ́n lọ́rùn ní Ọjọ́ igbende ...) [Áli 'Imrọ́n: 180][4]. [4] Bukhari ni o gbe e jade, pẹlu ounka (1338).

Sakaat sì jẹ dandan nínú oríṣi mẹrin: Àwọn kóró àti àwọn èso tí ó ń jáde láti inú ilẹ̀, àwọn ẹran-osin tí wọ́n ń jẹko kiri, wúrà àti fàdákà, àti àwọn nǹkan tí a pèsè kalẹ̀ fún òwò-ṣíṣe.

Atipe ọkọọkan ninu àwọn ẹka mẹrẹẹrin wọnyi ni o ní odiwọn kan pàtó, Sakah kò jẹ dandan lori ohun ti o ba kere si i. Odiwọn àwọn kóró àti àwọn èso ni: apo maarun, atipe Al-Wasq jẹ́ ọgọta sọọhu pẹlu sọọhu Anabi - ki ikẹ ati ọla Ọlọhun maa ba a - tí ó jẹ́ ọgọ́rùn-ún mẹ́ta sọọhu pẹlu sọọhu Anabi - ki ikẹ ati ọla Ọlọhun maa ba a - ninu dábìdun, èso àjàrà gbígbẹ, àlìkámà, ìrẹsì, ọkà bálì àti irúu wọn, èyí tí í ṣe ìkúnwọ́ mẹ́rin tí o jẹ ọwọ́ ọkùnrin oníwọ̀ntúnwọ̀nsì nínú ìṣẹ̀dá nígbàtí ọwọ́ rẹ̀ méjèèjì bá kún.

Ati pé ohun tí ó jẹ́ dandan nínú ìyẹn ni ìdákan nínú mẹ́wàá, bí ó bá jẹ́ pé àwọn ọ̀pẹ àti àwọn ohun ọ̀gbìn tí wan n bomi rin láìsí wàhálà, gẹ́gẹ́ bí omi òjò, àwọn odò, àwọn omi ìṣẹ́lẹ̀rú tí ó n ṣàn, àti irúu bẹ́ẹ̀.

Àmọ́ tí ó bá jẹ́ pé a fún un ní omi pẹ̀lú ìnáwó àti wàhálà: gẹ́gẹ́ bí àwọn ẹrọ ifá omí jáde láti inú kànga , àti àwọn ẹ̀rọ tí a fi ń gbé omi sókè, àti irú bẹ́ẹ̀, nígbà náà dájúdájú idaji idakan ninu ida mẹwa ni ó pọndandan nínú rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí hadisi ṣe fẹsẹ̀múlẹ̀ lórí ìyẹn láti ọ̀dọ̀ Òjíṣẹ́ Ọlọ́hun -kí ìkẹ àti ọlá Ọlọ́hun máa bá a-.

Ní ti Nisọbu ( òndiwan ìyè tí aní láti ni ) àwọn ẹran-ọ̀sìn tó ń jẹko, bíi Ràkúnmí, Maalu, àti Aguntan pẹ̀lú Ewúrẹ́, àlàyé fìnífíní wà lórí rẹ̀ nínú àwọn Hadith ododo láti ọ̀dọ̀ Òjíṣẹ́ Olóhun – kí ìkẹ́ àti ọlà Olóhun máa bá a –, ó sì ṣeé ṣe fún ẹni tí ó fẹ́ mọ̀ nípa rẹ̀ láti béèrè lọ́wọ́ àwọn onímọ̀ nípa ìyẹn, tí kì í bá ṣe pé a fẹ́ mú ọ̀rọ̀ kúrú ni, a o bá ti mẹ́nu bà á kí àǹfààní rẹ̀ ó lè pé.

Ní ti odiwọn fadaka, ó jẹ́ ọgọ́rùn-ún kan àti ogójì mithqāl(oṣuwọn) , iye rẹ̀ ní Dirham ti ilẹ̀ Saudi Arabia sì jẹ́ mẹ́rìndínlọ́gọ́ta Riyal.

Ati pe odiwọn goolu ogún miskọọlu (oṣuwọn) ni, ìwọ̀n rẹ̀ nínú Jínẹ́ẹ̀ ti Saudi sì jẹ́ Jínẹ́ẹ̀ mọ́kànlá àti ìdámẹta nínú ìdámẹje Jínẹ́ẹ̀ kan, pẹ̀lú girami ó sì jẹ́ méjìléláàádọ́rùn-ún girami, àti ohun tó jẹ́ dandan nínú àwọn méjèèjì ni ìdámẹrin ìdámẹwa fún ẹni tí ó ní odiwọn kan nínú wọn, tàbí nínú ọ̀kan nínú wọn, tí ọdún kan sì ti kọjá lórí rẹ̀.

Èrè n tẹle ipilẹ rẹ̀, kò sì nílò ọdún titun, gẹgẹ bi ìbísí àwọn ẹran ọ̀sìn tí ń jẹko ṣe n tẹle ipilẹ rẹ, kò nílò ọdún titun nígbàtí ipilẹ rẹ bá ti pé Nisab ( òndiwan tí a le yọ Sakah ) .

Nínú ìdájọ́ wúrà àti fàdákà ni àwọn owó oní takada tí àwọn ènìyàn ń fi ṣe ìbáṣe lónìí wà, yálà wọ́n pè é ní Dirham, tàbí Dinar, tàbí Dọla, tàbí àwọn orúkọ míìràn yàtọ̀ sí ìwọ̀nyẹn, tí iye rẹ̀ bá ti tó odiwọn fàdákà tàbí wúrà, tí ọdún kan sì ti kọjá lórí rẹ̀, Saka ti jẹ dandan nínú rẹ̀.

Ohun ọ̀ṣọ́ àwọn obìnrin nínú wúrà tàbí fàdákà ni wọn dapapọ̀ mọ́ owó, pàápàá jùlọ tí ó bá ti tó odiwọn, tí ọdún kan sì ti kọja lórí rẹ̀, Saka sì jẹ dandan nínú rẹ̀ bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé a pèsè rẹ̀ fún lílò tàbí yíyá lò, ní èyí tó tọ̀nà jùlọ nínú ọ̀rọ̀ méjèèjì àwọn onímọ̀; nítorí gbogboogbò ọ̀rọ̀ Ànábì - kí ikẹ Ọlọhun àti Ọlá Rẹ máa ba - : «Kò sí oní wúrà tàbí fàdákà kan tí kò san Saka rẹ̀; bí kò ṣe pé ní Ọjọ́ igbende, wọn yóò sọ wọ́n di awọ ìrìn pẹlẹbẹ iná fún un»[5]. Titi dé ìparí Hadīth tí ó ṣíwájú. [5] Muslim ni o gbe e jade (987).

Ati nitori nkan ti o fẹsẹmulẹ lati ọdọ Anabi -ki ikẹ ati ọla Ọlọhun maa ba a- pe o ri egbà ọwọ́ wura meji ni ọwọ arabinrin kan, ni o ba sọ pe: «Ǹjẹ́ o n yọ sàká èyí?». O sọ pé: Rárá. O sọ pé: «Ṣe yoo wu ọ ki Ọlọhun fi awọn mejeeji wọ̀ ọ́ ní ìgbànùwọ́ meji ti iná ni Ọjọ́ igbende!». Ni o ba sọ awọn mejeeji kalẹ, o si sọ pé: «Àwọn mejeeji jẹ́ ti Ọlọhun ati Ojiṣẹ Rẹ»[6]. [6] Abu Daa'ud ni o gbe e jade (1563), ati Nasa’i (2270), pẹlu ẹgbawa ti o da.

O si fi ẹsẹ rinlẹ lati ọdọ Ummu Salamọ ki Ọlọhun yọnu si i, pe dajudaju o maa n wọ àwọn ohun ọ̀ṣọ́ wura kan, o si sọ pe: iwọ ojiṣẹ Ọlọhun, ṣe ó jẹ́ àpẹpẹ ọrọ bí? O si sọ pe: «Èyíkéyìí (dúkìá) tí ó bá tó níwọ̀n zakaat, tí a sì yọ zakaat rẹ̀, kìí ṣe àpẹpẹ ọrọ mọn.»[7] pẹ̀lú àwọn Hadiisi míràn nipa ìtumọ̀ yii. [7] Abu Daa'ud ni o gbe e jade, pẹlu ounka (1564).

Ní ti àwọn nnkan òwò, ìyẹn àwọn ọjà tí a pèsè kalẹ̀ fún títà, a a maa gbéye lewan wọn ní ìparí ọdún, a sì maa n yọ ìdámẹ́rin ìdámẹ́wàá iye owó wọn, yálà iye owó wọn dọ́gba pẹ̀lú iye tí a fi rà wọ́n, tàbí kí ó pọ̀ jù ú lọ, tàbí kí ó dín kù; nítorí hadith Samurah, kí Allāh yọ́nú sí i, tí ó sọ pé: «Ojiṣẹ Ọlọhun - ki ikẹ ati ọla Ọlọhun maa ba a - máa ń pa wá ní àṣẹ pé kí á yọ Sakah jáde nínú ohun tí a pèsè fún títà [8]. [8] Abu Daa'ud ni o gbe e jade, pẹlu ounka (1562).

Wọ́n sì ka mọ́ èyí tí a sọ àwọn ilẹ̀ tí a pèsè kalẹ̀ fún títà, àwọn ilé-òkè, àwọn ọkọ̀, àwọn ẹ̀rọ ìfami, àti àwọn mìíràn tí ó yàtọ̀ sí ìyẹn nínú àwọn oríṣiríṣi ọjà tí a pèsè kalẹ̀ fún títà.

Amọ́ àwọn ilé tí a pèsè fún yíyá lo, ti kì í ṣe fún títà, Sakah wà nínú ere wọn tí ọdún bá yípo lórí rẹ̀, amọ́ ilé náà fúnrarẹ̀ kò sí Sakah lórí rẹ̀; nítorí pé a kò pèsè rẹ̀ fún títà. Bẹ́ẹ̀ náà ni àwọn ọkọ̀ ti ara ẹni àti ọkọ̀-èrò, kò sí Sakah lórí wọn tí a kò bá pèsè wọn fún títà, ṣùgbọ́n pé fún lílò ni olówó rẹ̀ rà wọ́n.

Atipe ti owo ba kojọpọ lọdọ ẹni ti o ni ọkọ ayọkẹlẹ-akero tabi omiran ti o si to odiwọn yíyọ Sakah , o pọndandan fun un lati yọ Sakah rẹ ti ọdun kan ba ti kọja lori rẹ, yala o pese rẹ kalẹ fun inawo ni, tabi fun igbeyawo, tabi fun rira ohun ìní gidi, tabi fun si san gbese, tabi ohun ti o yatọ si iyen ninu awọn erongba; nitori apapọ awọn ẹri ofin ẹ̀sìn ti o n tọka si dandan Sakah nibi iru eleyii.

Èyí tí ó sì tọ̀nà nínú àwọn ọ̀rọ̀ àwọn onímọ̀ ni pé gbèsè kì í dí yíyọ Saka lọ́wọ́ nítorí ohun tó ti ṣáájú nínú ọrọ wa .

Bákan náà ni dúkìá àwọn ọmọ òrukàn àti àwọn aṣiwèrè, Sakat jẹ dandan nínú rẹ̀ lọ́dọ̀ ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn onímímọ̀, tí ó bá ti tó odiwọn Nisab, tí ọdún kan sì ti yípo lórí rẹ̀, ó sì jẹ́ dandan lórí àwọn alámòójútó wọn láti yọọ́ jáde pẹ̀lú èròǹgbà fún wọn nígbàtí ọdún bá pé; fún gbogbo àwọn ẹ̀rí, bíi ọ̀rọ̀ Anọbi (kí ìkẹ́ àti ọlá Ọlọhun máa bá a) nínú hadith Mu'adh (kí Ọlọhun yọ́nú sí i) nígbàtí ó rán an sí àwọn ará Yemen pé: «Dájúdájú Ọlọhun ti ṣe yiyọ Sakah kan ní ọranyàn fún wọn nínú àwọn dúkìá wọn, tí a óò máa gbà lọ́wọ́ àwọn olówó wọn, tí a óò sì dá a padà fún àwọn tálíkà wọn»[9]. [9] Bukhōriy ni o gbe e jáde, pẹlu ounka (1395), àti Muslim, pẹlu ounka (19).

Ẹtọ Ọlọhun ní Sakah jẹ́ , kò yẹ kí a fi ṣe ojúṣaájú nínú rẹ̀ fún ẹni tí kò lẹ́tọ̀ọ́ sí i, bẹ́ẹ̀ ni kí ènìyàn má ṣe fi fa anfaani wá fún ara rẹ̀ tàbí kí ó fi yẹ aburú kúrò, bẹ́ẹ̀ ni kí ó má ṣe fi ṣọ́ dúkìá rẹ̀ tàbí kí ó fi yẹ ẹ̀gàn kúrò ní ara rẹ̀. Ṣùgbọ́n, ó pọndandan lórí Mùsùlùmí láti fi Sakah rẹ̀ fún àwọn tí wọ́n lẹ́tọ̀ọ́ sí i, nítorí pé wọ́n jẹ́ àwọn tó tọ́ sí i, kìí ṣe fún ète mìíràn, pẹ̀lú ọkàn mímọ́ sí i, àti ìfọkànsìn fún Ọlọhun nípa ìyẹn; kí ojúṣe rẹ̀ ó lè bọ́, kí ó sì lè lẹ́tọ̀ọ́ sí ẹ̀san tó pọ̀ yanturu àti ifi imii rọ́pò fún .

Dájúdájú Ọlọhun - Mímọ́ ni fún Un - ti ṣàlàyé àwọn ìran àwọn tí a ń fun ní Saka nínu Tira Rẹ Alápọ̀n-ọle, Ọlọhun Ọba ti ọla Rẹ ga sọ wipe: « Àwọn tí ọrẹ (Sakāh) wà fún ni àwọn aláìní, àwọn mẹ̀kúnnù, àwọn òṣìṣẹ́ Sakāh, àwọn tí ọkàn wọn fẹ́ gba ’Islām (ìyẹn àwọn tí wọ́n fẹ́ fi fa ọkàn wọn mọ́ra sínú ẹ̀sìn), àwọn ẹrú (fún gbígba òmìnira), àwọn onígbèsè, àwọn tó wà lójú ogun (ẹ̀sìn) Allāhu àti onírìn-àjò (tí agara dá). Ọ̀ran-anyàn ni láti ọ̀dọ̀ Allāhu ( Ọlọhun) . Allāhu sì ni Onímọ̀, Ọlọ́gbọ́n. [At-Taobah 60].

Ninu pipari ayah ọlọla yii pẹlu awọn orukọ nla mejeeji wọnyi, ifitonileti àti itaniji kan wa n bẹ lati ọdọ Ọlọhun -ti ọla ati ọpẹ n jẹ tirẹ- si awọn ẹru Rẹ lori pe Oun -ti ọla ati ọpẹ n jẹ tirẹ- ni Onimọ julọ nipa awọn ipo awọn ẹru Rẹ: ẹni ti o tọ si Sadaqa( Sakah) ninu wọn ati ẹni ti ko tọ si, Oun si ni Ọlọgbọn ninu ofin Rẹ ati kadara Rẹ, nitori naa ko nii gbe nnkankan si ibi kan ayafi si aye to yẹ fun un, koda bi apakan ninu awọn aṣiri ọgbọn Rẹ ba tilẹ pamọ fun apakan ninu awọn eniyan; ki ọkan awọn ẹru le bale si ofin Rẹ, ki wọn si juwọsilẹ fun idajọ Rẹ.

Ọlọhun ni a n bẹ ki O fi awa ati awọn Musulumi ṣe kongẹ fun agbọye ninu ẹsin Rẹ, ati ìṣòótọ́ ninu ìbáṣepọ̀ pẹlu Rẹ, ati ìsáré sí ohun ti yóò yọ Ọ́ nínú síwa, ati alaafia kuro nibi àwọn ohun ti n fa ibinu Rẹ, nitori Oun ni Ọba ti O ngbọ ti O si sunmọ wa.

Ki Ọlọhun ba wa ṣe ikẹ ati ọla Rẹ fun ẹru Rẹ ati ojiṣẹ Rẹ Muhammad ati awọn araale rẹ ati awọn saabe rẹ.

Aṣíwájú Gbogboogbo fún Ìdarí Ìwádìí Onímọ̀ Ìjìnlẹ̀

ati ṣiṣalaye idajọ, ofin ati ilana ẹsin, ati ipepe, ati ìtọ́nisọ́nà

Ọlọla wa Olumọ agba: Abdul Azeez ọmọ Abdullah ọmọ Bāz

Iwe ẹlẹẹkeji.

Nípa ọlá àti pataki ti n bẹ fun gbigba aawẹ oṣu Ramadan àti dide oru rẹ, pẹlu àlàyé lórí àwọn òfin pàtàkì tí ó lè farapamọ́ fún apá kan nínú àwọn ènìyàn.

Pẹlu orukọ Ọlọhun Ọba Ajọkẹ ayé Àṣàkẹ́ ọrun.

Lati ọdọ Abdul Azeez ọmọ Abdullah ọmọ Bāz, lọ si ọdọ ẹnikẹni ti o ba ri i ninu awọn Musulumi: Ki Ọlọhun tọ mi àti awọn náà si oju ọna awọn onigbagbọ ododo, ki O si fi jinde dede oore àti awọn náà lati ni oye agbọye Sunnah ati Al-Qur’ān. Āmīn

Ki àlàáfíà Ọlọhun, aanu ati ìbùkún Rẹ maa ba yín.

Lẹyìn bẹẹ: èyí jẹ́ imọran ni ṣókí tó jẹmọ́ ọlá ti n bẹ fun gbigba aawẹ oṣù Ramadan àti idide rẹ, àti ọlá ti n bẹ fun ṣiṣe ìdíje nínú rẹ pẹ̀lú àwọn iṣẹ́ olóore, pẹ̀lú ṣíṣe àlàyé àwọn òfin pàtàkì tí ó lè fara pamọ́ fún apá kan nínú àwọn ènìyàn.

Ó fi ẹsẹ rinlẹ láti ọdọ Ojiṣẹ Ọlọhun - kí ikẹ Ọlọhun àti ọlá Rẹ máa ba a - pé ó máa ń fún àwọn sàábà rẹ ní ìró ìdùnnú nípa wíwọlede oṣù Ramadan , ó sì máa ń fún wọn ní ìró, kí ikẹ àti ọlá Ọlọhun máa bá a, pé oṣù kan ni tí wọ́n máa ń sí àwọn ilẹ̀kùn àánú àti àwọn ilẹ̀kùn ọgbà idẹra kalẹ, tí wọ́n sì máa ń ti àwọn ilẹ̀kùn ina, tí wọ́n sì máa ń gbé àwọn èṣù dé mọ́lẹ̀, ó sì máa ń sọ pé: «Nígbàtí òru àkọ́kọ́ oṣù Ramadan bá ti dé, wọ́n yóò sí gbogbo ilẹkùn ọgbà idẹra kalẹ, wọn kò si ní tí ilẹkùn kan ṣoṣo nínú rẹ, bẹẹni wọn yóò ti gbogbo ilẹkùn iná, wọn kò sí ní ṣí ilẹkùn kan ṣoṣo nínú rẹ, bẹẹ sí ní wàn yóò gbé awọn èsù dé mọnlẹ, Olùpè kan yóò sì máa pè pé: Ìwọ olùwá rere sún mọ́bí, ìwọ olùwá aburú jáwọ́. Allahu sì ní àwọn tí ó máa dá sílẹ̀ kúrò nínú iná, èyí sì rí bẹ́ẹ̀ ní gbogbo òru»[1]. [1] Tirmidhiy ni o mu jade (682), ati Ibnu Mājah (1642).

O sọ – ki ikẹ ati ọla Ọlọhun maa ba a– pe: «Oṣù Rọmọdọ̄n ti dé bá yín, oṣù ìbùkún , Allāhu máa ń bò yín mọ́lẹ̀ nínú rẹ̀: Ó máa ń sọ ìkẹ́ kalẹ̀, Ó sì máa ń pa àwọn ẹ̀ṣẹ̀ rẹ́, Ó sì máa ń jẹ́ àdúà. Allāhu máa ń wo ìdíje rere yín nínú rẹ̀, Ó sì máa ń fi yín ṣóógó fún àwọn Mọlāika Rẹ̀; nítorí náà, ẹ jẹ́ kí Allāhu rí iṣẹ́ rere láti ọ̀dọ̀ yín; dájúdájú, oloribu ènìyàn ni ẹni tí wan se ìkẹ́ Allāhu leewọ fún nínú rẹ̀»[2]. [2] At-Tọbarọọniy lo mú jáde nínú tira Musnad rẹ, pẹlu ounka (2238).

Anọbi – ki ikẹ ati ọla Ọlọhun maa ba a– sọ pe: “Ẹni tí ó bá gba aawẹ Ramadan ni ti igbagbọ ati ireti ẹsan ni ọdọ Ọlọhun, wọn maa fi orí ẹsẹ rẹ ti o ṣáájú jin in, ati ẹni tí ó bá dìde ni Ramadan ni ti igbagbọ ati ireti ẹsan ni ọdọ Ọlọhun, wọn maa fi orí ẹsẹ rẹ ti o ṣáájú jin in, bẹẹ ni ẹni tí ó bá dìde ni oru Laelatul Kọdri ni ti igbagbọ ati ireti ẹsan ni ọdọ Ọlọhun, wọn yoo fi orí ẹṣẹ rẹ ti o ṣáájú jin in”[3]. [3] Bukhōriy ni o mu jáde pẹlu ounka (2014), àti Musilim pẹlu ounka (760).

Anọbi – ki ikẹ ati ọla Ọlọhun maa ba a– sọ pe: «Ọlọhun n sọ pé: Gbogbo iṣẹ́ ọmọ Adamọ ni a san ẹsan rere rẹ̀ ní ilọpo mẹ́wàá títí dé ilọpo ọgọ́rùn-ún méje, àyàfi aawẹ; Èmi ni mo ni ín, Èmi náà sì ni yóò san ẹsan rẹ̀; ó fi igbadun rẹ̀ sílẹ̀, àti oúnjẹ rẹ̀, àti ohun mímu rẹ̀ nítorí Mi. Ìdùnnú méjì ni n bẹ fún alaawẹ: ìdùnnú kan nígbà tí ó bá fẹ́ṣinu, àti ìdùnnú kan nígbà tí ó bá pàdé Olúwa rẹ̀. Dájú dájú oorun ẹnu alaawẹ ní oòrùn tí o daaju lọdọ Ọlọrun jù oòrùn lofinda Al-miski lọ»[4]. [4] Ibnu Mājah ni o mu jáde, (1638).

Awọn Hadiisi rẹpẹtẹ lo wa nípa ọlá tí nbẹ fún gbigba aawẹ Ramadan àti jiji loru láti yan nofilah ni òru rẹ, àti ọlá tí nbẹ fún aawẹ ní gbogbo gbòò.

O yẹ fun onigbagbọ ododo ki o lo anfani yii, oun naa ni: ore-ọfẹ ti Ọlọhun ṣe fun un lati de oṣu Ramadan; ki o yara si awọn iṣẹ-igbọran, ki o si ṣọra fun awọn iṣẹ buburu, ki o si sa ipa ni ṣiṣe ohun ti Ọlọhun ṣe ni ọran-anyan le e lori, pàápàá julọ awọn irun maraarun-un; nitori pe oun ni gbòngbo Esin Islam, oun si ni ọran-anyan ti o tobi julọ lẹhin awọn gbólóhùn ijẹri méjèjì. Nitori naa, ọranyan ti o wa lori gbogbo Musulumi okunrin ati obinrin ni mímójú to wọn ati kiki wọn ni awọn asiko wọn pẹlu itẹriba ati ifarabalẹ.

Ati pe ninu awọn ojúṣe rẹ pataki julọ lori awọn ọkunrin ni kìkì rẹ ni janmọọn ninu awọn ile Ọlọhun, eyiti Ọlọhun yọnda pe ki A gbe ga, ti A si n darukọ orukọ Rẹ ninu rẹ, gẹgẹ bi O ti sọ: (Ẹ kírun, ẹ yọ zakāh, kí ẹ sì dáwọ́tẹ orúnkún pẹ̀lú àwọn olùdáwọ́tẹ-orúnkún (lórí ìrun). [Suratul Baqara: 43], Ọlọhun tí Ọlá Rẹ ga tún sọ pé: Ẹ ṣọ́ àwọn ìrun (wákàtí márààrún) àti (ní pàápàá jùlọ) ìrun ààrin. Kí ẹ sì dúró kírun fún Allāhu ní olùbẹ̀rù Rẹ̀ (láì sì níí sọ̀rọ̀ tó jẹmọ́ tayé lórí ìrun). [Sūrah al-Baqarah: 238], O sọ pe: (Dájúdájú àwọn onígbàgbọ́ òdodo ti jèrè.) (Àwọn tó ń páyà (Allāhu) nínú ìrun wọn,) [Suuratul Muh’minuun: 1-2] titi de ibi tí o tí sọ pé: (àti àwọn tó ń ṣọ́ ìrun wọn; àwọn wọ̀nyẹn ni àwọn olùjogún, àwọn tó máa jogún ọgbà ìdẹ̀ra Firdaos. Olùṣegbére ni wọ́n nínú rẹ̀) [Surah Al-Mu’minûn: 9-11], Anọbi- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ máa bá a- sọ pe: «Adehun ti n bẹ laarin wa ati laaarin wọn ni Irun, ẹnití o ba gbe e ju silẹ ti di keferi»[5]. [5] Tirmidhiy ni o mu jade (2621), ati Ibnu Mājah (1079).

ọran-anyan tó ṣe pàtàkì jùlọ lẹyin irun si ni yíyọ Zakat, gẹ́gẹ́ bí ó ti sọ pé: (Àwa kò sì pa wọ́n ní àṣẹ kan bí kò ṣe pé kí wọ́n jọ́sìn fún Allāhu lẹ́ni tí yóò máa ṣe àfọ̀mọ́ ẹ̀sìn fún Un, lẹ́ni tí yóò dúró ṣinṣin nínú ẹ̀sìn. Kí wọ́n kírun, kí wọ́n sì yọ Zakāh. Ìyẹn sì ni ẹ̀sìn tó fẹsẹ̀ rinlẹ̀) [Al-Bayyinah: 5], Ọlọhun Ọba- ti ọla Rẹ ga- sọ pe: Ẹ kírun. Ẹ yọ Zakāh. Ẹ tẹ̀lé Òjíṣẹ́ náà nítorí kí A lè kẹ yín. [Sūratun Nūr: 56].

Dájúdájú Tira Ọlọhun títóbi àti Sunna Ojiṣẹ Rẹ̀ ọlọla ti tọ́ka sí i pé ẹnikẹ́ni tí kò bá yọ Zakah dúkìá rẹ̀, a ó fi í jẹ ẹ́ níyà ní Ọjọ́ Àjíǹde.

Nnkan ti o ṣe pataki julọ lẹyin Irun ati Sakah ni gbigba aawẹ Ramadan, oun si ni ọkan ninu awọn origun Isilaamu marun-un ti a darukọ ninu ọrọ Anabi - ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a-: «Wọ́n mọ Islaam pa lórí nǹkan márùn-ún: ìjẹ́rìí pé kò sí ẹni tí ìjọsìn ododo tọ́ sí àyàfi Allāhu àti pé dájúdájú Muhammad òjíṣẹ́ Ọlọ́run ni, àti gbígbé irun dúró, àti yíyọ Sakah, àti gbígba ààwẹ̀ Ramadān, àti ṣíṣe Hajj sí Ilé Ọlọ́run»[6]. [6] Bukhari ni o mu jáde pẹlu ounka (8), ati Muslim pẹlu ounka (16).

Ó sì jẹ́ dandan fún Mùsùlùmí láti ṣọ́ ààwẹ̀ rẹ̀ àti ìdúró-nafilah rẹ̀ kúrò nínú ohun tí Ọlọ́hun ṣe ní èèwọ̀ fún un nínú àwọn ọ̀rọ̀ àti iṣẹ́; nítorí pé ọgbọn àti òye tí ó wà nídìí ààwẹ̀ gbígbà ni ìtẹríba fún Ọlọ́hun - Mímọ́ ni fun Un -, àti gbígbé àwọn ohun èèwọ̀ Rẹ̀ ga, àti ìjà ẹ́mi lógún lórí yíyapa kúrò nínú ìfẹ́-inú rẹ̀ ní ti ìtẹríba fún Olúwa rẹ̀, àti kíkọ́ ọ ní sùúrù lórí ohun tí Ọlọ́hun ṣe ní èèwọ̀. Kii se èròngbà aawẹ ni kí a fi oúnjẹ àti ohun mímu sílẹ̀ àti gbogbo àwọn ohun yòókù tí ó ń ba ààwẹ̀ jẹ́ nìkan ; Nítorí èyí ni ó ṣe fẹsẹ̀ múlẹ̀ láti ọ̀dọ̀ Òjíṣẹ́ Ọlọ́hun (kí ìkẹ́ àti ọlà Ọlọ́hun máa bá a) pé ó sọ pé: «Aawẹ jẹ́ ààbò, ni ọjọ́ aawẹ ẹnikan nínú yín tàbí tí ẹni kọkan yín ba ngbà aawẹ, kí ó má ṣe sọ ọ̀rọ̀ ìsọkúsọ, kí ó má sì pariwo, tí ẹnikan bá bù ú tàbí tí ó fẹ́ bá a jà, kí ó wí pé: ‘Dájúdájú alaawẹ ni mí’»[7]، O si tún ni àlàáfíà lati ọdọ rẹ - ki ikẹ ati ọla Ọlọhun maa ba a – wipe o sọ pe: «Ẹnikẹ́ni tí kò bá fi ọ̀rọ̀ èké, àti ṣíṣe iṣẹ́ pẹ̀lú rẹ̀, àti ìwà àìmọ̀kan sílẹ̀, Ọlọhun kò nílò kí ó fi oúnjẹ rẹ̀ àti ohun mímu rẹ̀ sílẹ̀»[8]. A ti mọ̀ pẹ̀lú àwọn ọ̀rọ̀ wọnyi àti àwọn mìíràn pé ohun tó jẹ́ òranyàn lórí aláàwẹ ni láti ṣọ́ra kúrò nínú gbogbo nǹkan tí Ọlọ́hun ṣe ní eewọ̀, àti láti pa gbogbo nǹkan tí Ọlọ́hun ṣe ní dandan mọ́. Pẹ̀lú ṣíṣe bẹ́ẹ̀ ni a fi ń retí àforíjìn, ìtúsílẹ̀ kúrò nínú iya ina, àti ìtẹ́wọ́gbà aawẹ àti ìrun fún un. [7] Bukhari ni o mu jade pẹlu ounka (1904), àti Nasaa'i pẹlu ounka (2537). [8] Bukhari ni o mu jade pẹlu ounka (1804), ati Abū Dāwūd pẹlu ounka (2362).

Ati pe àwọn àlámọ̀rí kan wà tí ó lè pamọ́ si àwọn ènìyàn kan:

Lára rẹ̀ ni: pé ohun tí ó jẹ ọranyàn fún Musulumi ni pé kí ó gba aawẹ ní ti ìgbàgbọ́ àti ìrètí ẹ̀san, kìí ṣe ti ṣekarimi tàbí ṣekagbọmi, tàbí fífara wé àwọn ènìyàn, tàbí títẹ̀lé àwọn ẹbí rẹ̀ tàbí àwọn ará ìlú rẹ̀. Ṣùgbọ́n, ohun tí ó jẹ ọranyàn lórí rẹ̀ ni pé, kí ohun tí ó ń sún un sí gbígba aawẹ jẹ́ ìgbàgbọ́ rẹ̀ pé dájúdájú Ọlọhun ti sọ ọ́ di ọranyàn lé e lórí, àti ìrètí ẹ̀san rẹ̀ lọ́dọ̀ Olúwa rẹ̀ nínú rẹ̀. Báyìí náà ni ìdúró Ramadan, ó yẹ kí Musulumi ó ṣe é ní ti ìgbàgbọ́ àti ìrètí ẹ̀san, kìí ṣe fún ìdí mìíràn; nítorí èyí ni ó fi sọ -ìkẹ Ọlọhun àti ọlá Rẹ̀ máa bá a- pé: “Ẹni tí ó bá gba aawẹ Ramadan ni ti igbagbọ ati ireti ẹsan ni ọdọ Ọlọhun, wọn maa fi orí ẹṣẹ rẹ ti o ṣáájú jin in, ati ẹni tí ó bá dìde ni Ramadan ni ti igbagbọ ati ireti ẹsan ni ọdọ Ọlọhun, wọn maa fi orí ẹṣẹ rẹ ti o ṣáájú jin in, ati ẹni tí ó bá dìde ni oru abiyi ni ti igbagbọ ati ireti ẹsan ni ọdọ Ọlọhun, wọn maa fi orí ẹṣẹ rẹ ti o ṣáájú jin in”[9]. [9] Bukhōriy ni o mu jáde, pẹlu ounka (2014), àti Muslim, pẹlu ounka (760).

Lára àwọn nǹkan tí ìdájọ́ rẹ̀ le farasin fún apá kan àwọn ènìyàn ni: ohun tí ó le ṣẹlẹ̀ sí ẹni tí ó ń gba aawẹ bíi ọgbẹ́, tàbí ẹjẹ imú, tàbí eebi, tàbí gbígbé omi mí tàbí epo bẹntiróò sí ọ̀fun rẹ̀ láìjẹ́ ìfẹ́-inú rẹ̀, gbogbo àwọn nǹkan wọ̀nyí kò ní ba aawẹ jẹ́, ṣùgbọ́n ẹni tí ó bá mọ̀ọ́mọ̀ mú eebi jáde, aawẹ rẹ̀ yóò bàjẹ́; nítorí ọ̀rọ̀ Ànábì: «Ẹnikẹ́ni tí èèbì bá gbé mì, kò sí sisan awẹ padà fún un, ṣùgbọ́n ẹni tí ó bá mọ̀ọ́mọ̀ bì, sisan aawe wà lórí rẹ̀»[10]. [10] Tirmidhiy ni o mu jade, pẹlu ounka (720), ati Ibnu Mājah, pẹlu ounka (1676).

Nínú ìyẹn ni: ohun tí ó lè ṣẹlẹ̀ sí aláàwẹ̀ nínú sísun wíwẹ janaba rẹ̀ síwájú di ìgbà lẹ́yìn yíyọ alufajari, àti ohun tí ó lè ṣẹlẹ̀ sí ọdọ apá kan àwọn obìnrin nínú sísun wíwẹ imọra nnkan oṣù tàbí ti ẹ̀jẹ̀ ìbímọ síwájú di lẹ́yìn yíyọ alufajari nígbà tí ó bá ti mọ ṣíwájú alufajari, dandan ni fún un kí ó gba àwẹ̀, kò sì sí ìdínà fún un láti sun wíwẹ rẹ̀ síwájú di ẹ́yìn yíyọ alufajari, ṣùgbọ́n kò gbọdọ̀ sun ún síwájú di yiyọ oòrùn, kàkà bẹ́ẹ̀, ó jẹ́ dandan fún un kí ó wẹ, kí ó sì kirun al-fajri ṣíwájú yíyọ oòrùn, Bẹẹ gẹgẹ ni oni janaba, ko gbọdọ fa iwẹ sẹyin titi di lẹyin yiyọ oòrùn, kàkà bẹẹ o jẹ dandan fún un kí o wẹ kí o si ki irun Fajr siwaju yiyọ oòrùn, o si jẹ dandan fun ọkunrin lati yára si ìyẹn ki o ba le bá irun Fajr pẹlu jamaa.

Nínú awọn nǹkan tí kò níí ba aawẹ jẹ́ ni: àyẹ̀wò ẹjẹ, àti gbígba abẹ́rẹ́ èyí tí kìí ṣe fún oúnjẹ ara, ṣùgbọ́n sísún un síwájú di alẹ́ ló dára jù, ó sì fi ọkàn balẹ̀ jù tí èyí bá rọrùn; nítorí ọ̀rọ̀ Ànábì - ki ikẹ ati ọla Ọlọhun maa ba a: «Gbe ohun ti nse ọ ni iyemeji jusilẹ, ki o lọ sibi ohun ti ko se ẹ ni iyemeji»[11]. [11] Tirmidhiy ni o mu jade, pẹlu ounka (2518).

ati ọ̀rọ̀ Anabi - ki ikẹ ati ọla Ọlọhun maa ba a - «Ẹnikẹni ti o ba ṣọra fún àwọn nǹkan ìríjú, dájúdájú ó ti sọ ẹsin rẹ àti ọmọlúwàbí rẹ»[12]. [12] Bukhōriy ni o mu jáde, pẹlu ounka (52), àti Muslim, pẹlu ounka (1599).

Lára àwọn ọ̀rọ̀ tí ìdájọ́ rẹ̀ pamọ́ fún apá kan àwọn ènìyàn ni: aì fi ara balẹ̀ nínú ìrun, yálà ó jẹ́ ìrun ọranyan tàbí ìrun nafila. Dájúdájú àwọn Hadith ti o ní àlàáfíà ti fihàn láti ọ̀dọ̀ Òjíṣẹ́ Ọlọ́hun, kí ìkẹ́ àti ọlà Ọlọ́hun máa bá a, pé dájúdájú fifi ara balẹ̀ jẹ́ origun kan nínú àwọn origun ìrun, tí ìrun kò sì ní sí láìsí i. Ó sì jẹ́ dídúró jẹ́ẹ́ nínú ìrun àti irẹlẹ nínú rẹ̀ àti aìní ìkánjú, títí gbogbo oríkèé ara yóò fi padà sí àyè rẹ̀. Ọ̀pọ̀lọpọ̀ nínú àwọn ènìyàn ni ó máa ń ki ìrun Tarawih ní oṣù Ramadan ní irú ìrun kan tí wọn kò fi ọkàn sí, tí wọn kò sì fi ara balẹ̀ nínú rẹ̀; kàkà bẹ́ẹ̀, wọ́n kàn ń ṣà á ni bí adìyẹ ṣe ń jẹun. Irun tí a bá kì lórí irúfẹ́ ọ̀nà báyìí, ó bàjẹ́, ẹni tí ó sì kì í jẹ́ ẹlẹ́ṣẹ̀, kò sì ní ẹ̀sán kankan fún un.

Lara awọn nkan ti idajọ rẹ le pamọ fun apakan awọn eniyan ni: di daba awọn kan pe dajudaju Taraawihi ko yẹ ki o dinku sí ogun rakah, ati riro awọn miran pe ko yẹ ki a ṣe alekun si i ju rakah mọkanla tabi mẹtala lọ. Gbogbo eyi jẹ ero ti ko ba oju mu, ṣugbọn aṣiṣe ni ti o tako awọn ẹri.

Àwọn hadith to ni àlàáfíà ti fẹsẹ̀ múlẹ̀ láti ọ̀dọ̀ Òjíṣẹ́ Ọlọhun - kí ìkẹ́ àti ọla Ọlọhun máa bá a - pé ìgbà laààyè wà nínú irun òru, kò sì ní òǹkà kan pàtó tí kò yẹ kí á yapa kúrò níbẹ̀. Bí kò ṣe pé ó ti fẹsẹ̀ múlẹ̀ láti ọ̀dọ̀ rẹ̀ - kí ìkẹ́ àti ọlá Ọlọhun máa bá a - pé ó máa ń ki rakah mọ́kànlá ní alẹ́, nígbà míràn ó máa ń ki rakah mẹ́tàlá, àti pé nígbà míràn ó máa ń ki èyí tó kéré sí ìyẹn, nínú Ramadan àti ní ìgbà mìíràn. Nígbàtí wọn sì bi í léèrè nípa irun òru, ó sọ pé: «Meji meji ni, ti ẹnikọọkan yin ba bẹru ki asunba bọ fun un, kí o ki rakaa eyọkan tí yio jẹ witiri fun un fun ohun ti o ti ki»[13]. Imam Bukhari ati Muslim lo gba a wa tí wọn si panupọ lórí lilalaafia rẹ . [13] Bukhōriy ni o mu jáde, pẹlu ounka (946), àti Musilim, pẹlu ounka (749).

Kò sì sàmì sí iye rakaah kan pàtó, yálà nínu Ramadan tàbí yàtọ̀ si i, nitori idi eyi ni awọn Sọhābah ṣe kirun ni asiko Umar – ki Ọlọhun yọnu si i – ni awọn ìgbà kan rakaah mẹtalelogun, àti ní awọn miiran rakaah mọkanla, gbogbo ìyẹn sì fìdí múlẹ̀ lati ọdọ Umar – ki Ọlọhun yọnu si i – àti lati ọdọ awọn Sọhābah ni asiko rẹ.

Apá kan nínú àwọn Salaf (awọn ẹni síwájú nínú ẹṣin) a máa kirun rakaah mẹ́rìndínlógójì nínú Ramadan, wọ́n sì máa ń fi rakaah mẹ́ta ṣe witri, nígbàtí àwọn mìíràn a máa kirun ọ̀kànlélógójì. Shekhul Islam Ibnu Taimiyyah àti àwọn mìíràn yàtọ̀ sí i nínú àwọn oní mimọ̀ ni wọ́n gba èyí wá láti ọ̀dọ̀ wọn. Gẹ́gẹ́ bí ó ṣe mẹ́nu kàn án - kí ìkẹ́ Ọlọ́hun máa bá a - pé dájúdájú ọ̀rọ̀ náà ní ààyè nínú èyí, ó sì tún mẹ́nu kàn án pé ohun tó dára jùlọ fún ẹni tí ó bá fa kíkà Qur'an, rukuu( itẹriba ) àti sijdah ( ifori kanlẹ ) gùn ni pé kí ó dín iye rakah kù, ẹni tí ó bá sì ṣe é ní fùfúyẹ́, yóò ṣe àlékún sí iye rakah. Èyí ni ìtumọ̀ ọ̀rọ̀ rẹ̀ - kí ìkẹ́ Ọlọ́hun máa bá a -.

Ẹnikẹ́ni tó bá ṣe àgbéyẹ̀wò Sunna rẹ̀ - ki ikẹ ati ọla Ọlọhun maa ba a - yóò mọ̀ pé ohun tó dára jù lọ nínú gbogbo èyí ni kíkí raka mọ́kànlá tàbí mẹ́tàlá nínu oṣù Ramadan àti yàtọ̀ sí i; nítorí pé èyí ló bára mu pẹ̀lú iṣẹ́ Ànọ́bì - ki ikẹ ati ọla Ọlọhun maa ba a - ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìgbà, àti pé óhun ni o rọrùn jùlọ fún àwọn olùkírun, ó sì súnmọ́ ipaya àti ìfarabalẹ̀. Ẹnikẹ́ni tó bá sì fi kún un, kò sí àìṣedéédéé nínú rẹ̀, kò sì sí ohun ìríra nínú rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣíwájú.

Eyi ti o daa julọ fun ẹni ti o kirun pẹlu Imam ninu irun iduro Ramadan ni ki o maṣe kuro ayafi pẹlu Imam; nítorí ọrọ Anabi: «Dajudaju ọmọniyan ti o ba ba Imọmu duro titi ti yoo fi pari Irun, Ọlọhun yìí kọ ẹsan iduro oru kan fun un delẹ fún »[14]. [14] Tirmidhiy ni o mu jade (806), ati Abu Daa'ud (1375).

Wan tí se ni ìlànà ẹṣin fún gbogbo àwọn Musulumi láti ṣe ìgbìyànjú nínú àwọn orísirísi ìjọsìn nínu osù alápọ̀n-ọle yii, bíi kíkí irun àtinúdá, àti kíkà Alukurāni pẹ̀lú àròjinlẹ̀ àti ìlóye, àti pípọ̀ ní ṣíṣe gbólóhùn “SubhanAllahi”, àti gbólóhùn “lā ilāha illā Allāhu”, àti gbólóhùn “AlhamduliLlāhi”, àti ṣíṣe gbólóhùn “Allāhu Akbar”, àti títọrọ àforíjìn, àti ṣíṣe àwọn àdúà tí ó bá òfin mu, àti pípaṣẹ ohun rere àti kíkọ ohun burúkú, àti ìpèpè sí ọ̀dọ̀ Ọlọ́hun, àti dídá àwọn aláìní àti mẹ̀kúnnù laraya, àti ṣíṣe ìgbìyànjú nínú ṣíṣe rere sí àwọn òbí méjèèjì, àti dida okùn-ìbátan papọ, àti ṣíṣe àpọ́nlé fún aládùúgbò, àti ṣíṣe àbẹ̀wò sí aláìsàn, àti àwọn orísirísi iṣẹ́ rere mìíràn yàtọ̀ sí ìwọ̀nyí; nítorí ọ̀rọ̀ rẹ̀ (kí ìkẹ́ àti ọlà Ọlọ́hun máa bá a) nínú Hadith tí ó ṣáájú: «Ọlọhun maa n wo ìfigagbaga yín nínú rẹ̀, Ó sì maa n fi yín se iyanran si àwọn Mọlaika Rẹ̀; nítorí náà, ẹ jẹ́ kí Ọlọhun rí oore láti ọ̀dọ̀ yín, nítorí pé dájúdájú, oloribu ni ẹni tí wan se aanu Ọlọhun ni eewọ fún nínú rẹ̀»[15]. [15] At-Tobarooniy ni o mu jáde ninu Musnad rẹ̀, pẹlu ounka (2238).

ati nitori eyi ti wọn gba wa lati ọdọ rẹ - ki ikẹ ati ọla Ọlọhun maa ba a - pe o sọ pe: «Ẹni tí ó bá sunmọ mi pẹlu siṣe iṣẹ́ rere kan nínú rẹ̀, ó dàbí ẹni tí ó ṣe iṣẹ́ ọ̀ranyàn kan nínu àsìkò mí to yatọ si ni , àti ẹni tí ó bá ṣe iṣẹ́ ọ̀ranyàn kan nínú rẹ̀, ó dàbí ẹni tí ó ṣe iṣẹ́ ọ̀ranyàn àádọ́rin ní asiko míràn ni »[16]. [16] Ibnu Khuzaimah ni o mu jáde nínu Sọhīhi rẹ̀, pẹlu onka (1887).

Àti nítorí ọrọ Anọbi -kí ikẹ Ọlọhun àti ọlá Rẹ máa ba a- nínú Hadiisi tí ó ní àlàáfíà pé: «Umrah kan nínú Ramadan ṣe déédé Hajj, tàbí ó ní: Hajj pẹlu mi»[17]. [17] Bukhari ni o mu jade pẹlu ounka (1863).

Àwọn Àádísí àti àwọn ìtọpasẹ̀ pọ̀ lọ́pọ̀lọpọ̀ tí wọ́n ń tọ́ka sí pé wọn tise ni ìlànà ẹṣin láti ṣe ìdíje àti ìfigagbaga nínú oríṣiríṣi iṣẹ́ rere ní oṣù ọlọ́lá yìí.

Ọlọhun ni a n bẹ ki O fi awa ati gbogbo awọn Musulumi ṣe kongẹ gbogbo ohun ti yoo yọ Ọ ninu, ki O si gba ààwẹ̀ wa àti ìdúró-nafilah wa, ki O si tun àwọn ipò wa ṣe, ki O si sọ gbogbo wa yọ kúrò níbi àwọn ìdàrúdàpọ̀ aṣinilọ́nà. Bákan náà a n bẹ Ẹ́ - Mímọ́ ni Fún Un - pé kí O tun àwọn adarí àwọn Mùsùlùmí ṣe, ki O si jẹ ki ohùn wọn ṣe ọ̀kan lórí òdodo. Oun ni olukapa lórí rẹ̀.

Ki alaafia ati ikẹ Ọlọhun ati ìbùkún Rẹ maa ba yin.