المختصر في صفة الحج

المختصر في صفة الحج

Ọrọ ní ṣókí nipa bí a ṣe nṣe iṣẹ ìjọsìn Hajj Ọpẹ ni fún Ọlọrun Olúwa gbogbo agbanlaaye, kí ikẹ Ọlọhun àti ọla Rẹ maa ba Anọbi wa Muhammad àti awọn ará ilé rẹ àti awọn ọmọ lẹyìn rẹ lapapọ.

Language: lang_yo
Prepared by: Igbimọ awọn onimimọ to wa ninu ijọ ti n fi orisirisi ede ṣiṣẹ lori ọrọ Islam.
Version: 3.0
Translations 44
Amharic Assamese Azerbaijani Bambara +40
Attachments 7
PDF
Audio
Video
+3

Ọrọ ní ṣókí nipa bí a ṣe nṣe iṣẹ ìjọsìn Hajj Ọpẹ ni fún Ọlọrun Olúwa gbogbo agbanlaaye, kí ikẹ Ọlọhun àti ọla Rẹ maa ba Anọbi wa Muhammad àti awọn ará ilé rẹ àti awọn ọmọ lẹyìn rẹ lapapọ.

Lẹyin naa:

Eleyi ni àkànṣe ẹkọ ní ṣókí nipa síse isẹ ìjọsìn Hajj, o wuwa lati ṣe àlàyé ọpọ awọn nkan tí ẹniti o fẹ ṣẹ Hajj ni bukata sí nínú rẹ.

Ọlọhun Allah ni a nbẹ kí o ṣeé ni nkan tí a se nítorí Rẹ nìkan tí a si fi wa ojurere Rẹ, kí o si jẹ kí o wúlò fún apapọ gbogbo Musulumi.

Igbimọ awọn onimimọ to wa ninu ijọ ti n fi orisirisi ede ṣiṣẹ lori ọrọ Islam.

ọ̀rọ̀ ìṣáájú

Awọn majẹmu gbígba ìjọsìn.

Ìjọsìn kò ní di gbígbà wọlé lọdọ Ọlọhun tí ọlá Rẹ ga jùlọ ayaafi pẹlu majẹmu méjì ni:

Kí a ṣe e nítorí Ọlọhun nìkan: ohun ni kí a fi ijọsin wa ojurere Ọlọhun àti Ọjọ ìkẹyìn, Ọlọhun tí Ọlá Rẹ ga sọ pé: (Àwa kò pa wọ́n ní àṣẹ kan bí kò ṣe pé kí wọ́n jọ́sìn fún Allāhu lẹ́ni tí yóò máa ṣe àfọ̀mọ́ ẹ̀sìn fún Un, lẹ́ni tí yóò dúró ṣinṣin nínú ẹ̀sìn ...)[1]", [Al-bayyinah: 5]. [1] ìtumọ rẹ nipe: kí o doju ẹṣin rẹ kọ Ọlọhun, kí o si sẹri kúrò níbi nkan tí o yatọ si I. Tira Tafsiri As-sa'diy (ojú ewé 538)

Anọbi kí ikẹ Ọlọhun àti ọla Rẹ máa ba sọ pé: "Àwọn iṣẹ́ pẹlu àníyàn ni, ohun ti ọmọniyan ba gba lero ni yoo maa jẹ tiẹ̀" [2]. [2] Al-Bukhari lo gba a wa, pẹlu onka (1), àti Muslim pẹlu onka (1907).

Titẹ le anọbi níbi iṣẹ Hajj náà nibi ọrọ ati iṣẹ rẹ̀, anọbi kí ikẹ Ọlọhun àti ọla Rẹ máa ba a sọ pé: "Ẹni kẹni ti o ba da adadaalẹ kalẹ sinu alamọri wa yii ninu nnkan ti ko si nibẹ, wọn maa da a pada ni " [3]. Nínu ẹgbawa kan: "Ẹni kẹni ti o ba ṣe iṣẹ kan ti ko si àṣẹ wa nibẹ, wọn maa da a pada ni" [4]. [3] Al-bukhari lo gbaa wa, pẹlu onka (2697), àti Muslim, pẹlu onka (1718). [4] Muslim lo gbaa wa, pẹlu onka (1718)

***

Alakọkọ: Awọn idajọ ààyè dida àníyàn iṣẹ Hajj:

Al-Mawaqeet: ni awọn ààyè tí anọbi se adayanrí rẹ - kí ikẹ Ọlọhun àti ọla rẹ máa ba a - láti le bẹẹrẹ ìjọsìn fún ẹni tí o fẹ se ìjọsìn Hajj tabi Umrah.

Ẹnikẹni tí o ba rekọjá níbi ọkan nínú rẹ ní ẹni tí o gbèrò lati ṣe Hajj tàbí Umrah: dandan ni fun kí o daniyan ìjọsìn naa níbi ààyè náà, ko letọ fun láti kọjá ààyè náà lai daniyan.

Ẹni tí o ba sun mọn Makkah ju awọn ààyè wọnyi lọ: dájúdájú ààyè tí yóò ti dàníyàn ijọsin náà ni ààyè rẹ tí o wa, ibẹ ni yóò ti dàníyàn Hajj àti Umrah.

Ṣugbọn awọn ará Makkah ati awọn tí wọn ngbe ibẹ: wọn yóò dàníyàn ìjọsìn Hajj tiwọn ni ilú Makkah, ṣugbọn Umrah: wọn yóò jáde lọsí ìta Makkah tí wọn yóò sì lọ dàníyàn ibẹrẹ ìjọsìn Hajj níbẹ, gẹgẹbi kí wọn gbéra ni Tan'iim àti ibo míràn ti o jọ ọ.

Ẹni tí o ba wà nínú ọkọ òfurufú: yóò daniyan iṣẹ ijọsin nigbati ọkọ òfurufú náà ba ti wa ni ògángán ààyè idaniyan iṣẹ Hajj àti Umrah, yóò si mura bẹẹ ni yóò wọ aṣọ ibẹrẹ ìjọsìn Hajj àti Umrah lẹsẹkẹsẹ, kò tọ fún láti lọọ lára di igba tí yóò to sọ kalẹ ní ibùdókọ Ofurufu, o si rọrun fun kí o ko akoyawọ fún kí o ti daniyan síwájú ki o to dé ògángán ààyè idaniyan nítorí ìbẹrù kí o mọn kọja ààyè idaniyan, nítorí yiyara ọkọ ofurufu.

Ẹlẹẹkeji: awọn oríṣiriṣi iṣẹ ìjọsìn Hajj àti awọn ìdájọ rẹ:

Mẹta ní ìjọsìn Hajj Pin sí: ṣíṣe pẹlu igbadun, aladaṣe, àti alase papọ.

Ṣíṣe pẹlu igbadun ni o lọla jù fún ẹni tí kò ní pa nkan ọsin fun itọrọ, òhun ni kí a dàníyàn ìjọsìn Umrah nínú awọn osu ijọsin Hajj, kí o si ṣe irọkirika ile Ọlọhun, kí o si ṣe ipọsẹsẹ láàrin Sọfa àti Marwah, kí o si parí iṣẹ ìjọsìn Umrah, lẹyìn bẹẹ kí o wa padà da àníyàn iṣẹ ìjọsìn Hajj pẹlu gbígbé harami ní ọdún kan náà.

Al-Ifraad ni kí a gbe harami ibẹrẹ iṣẹ ìjọsìn Hajj nìkan ṣoṣo, tí o ba de Makkah wọn ti se ni ìlànà anọbi pé ki o rọkirika ile Ọlọhun fún ti dide ile Ọlọhun lẹyìn náà ni yóò ṣe ipọsẹsẹ láàrin Sọfa àti Marwah fún ti ìjọsìn Hajj, koni tii fa irun ori rẹ bẹẹ ni koni gẹ kosi ni tii bọ aṣọ harami rẹ, tí o ba lọ ṣe ipọsẹsẹ ṣugbọn yóò máa bẹ pẹlu harami rẹ titi yóò fi di eyin ìgbàtí o ba ju òkuta tan ni 'Aqabah ni ọjọ Ọdun, tí o ba si lọ ipọsẹsẹ ti Hajj lara di ẹyín ìgbàtí o ba fẹ se irọkirika ile Ọlọhun fún isẹ ìjọsìn Hajj kò sí aburu nibẹ.

Al-Qiraan: ohun ni kí a gbe asọ harami àti àníyàn Umrah papọ mọn ti Hajj, ti yoo sí sọ pe: (Mojẹpe Irẹ Ọlọhun láti ṣe Umrah àti Hajj).

Iṣẹ Hajj ti ẹnití o pa Hajj papọ mọ Umrah àti ẹniti o da Hajj se isẹ kan náà ni, o kan jẹ pé ẹniti o pa Hajj pọ mọ Umrah, dandan ni kí o pa ẹran ìjọsìn, bẹẹ si ni ẹni tí o da Hajj se kii se dandan ni kí o pa ẹran ìjọsìn.

Ẹlẹẹkẹta: Bí a se ngbe harami (eyi ni idaniyan iṣẹ Hajj) àti awọn ìdájọ rẹ:

Awọn nkan tí nbọ yii ni wọn se ni ìlànà ìjọsìn fún ẹni tí o fẹ bẹrẹ iṣẹ ìjọsìn Hajj (tí o fẹ gbé harami):

1. Wiwẹ, ohun ni o jẹ ìlànà Anọbi tí wọn kan nípa fún Ọkùnrin àti Obìnrin titi o fi kan obìnrin tí nṣe nkan oṣù lọwọ àti èyí tí o wa nínú ẹjẹ ibimọ.

2. Lilo èyí tóní oòrùn ju nínú lọfinda tàbí ipara tàbí nkan mii sí orí rẹ àti irungbọn rẹ, kí irú ìpara bẹẹ sẹku sí orí rẹ lẹyìn tí o ti gbé harami tan ko le kó àìda kankan ba, ṣugbọn obìnrin kò lẹtọ fun láti lo nkan oloorun bi lọfinda nítorí ki awọn ọkunrin àjòjì má le máa gbọ oorun náà.

3. Wíwọ aṣọ harami, ohun ni aṣọ iro àti idabora, nínú ìlànà anọbi ni kí mejeeji je aṣọ funfun tí o mọ daada tàbí kí o jẹ titun. Bẹẹ ni obirin yóò máa gbé harami pẹlu asọ tí o ba wu yatọ sí aṣọ tí yóò máa fi ara rẹ ati ọsọ rẹ hàn, ayaafi pé yóò jina sí wíwọ ìbòjú àti ibọwọ mejeeji, yóò sí bo ojú rẹ ati ọwọ rẹ mejeeji pẹlu nkan tí o yato si èyí tí a sọ un.

4. Kí a bẹrẹ iṣẹ Hajj pẹlu gbígbé harami lẹyìn irun kiki tí o ba òfin ẹṣin mu, ki baa jẹ Irun ọranyan tàbí irun Naafilah (àfikún), eléyun kii se ọranyan.

Tí yóò si mọ sọ bayi pé: (mojẹpe rẹ Ọlọhun fún iṣẹ ìjọsìn Umrah) tí o ba jẹpé ẹni tí o nṣe Umrah ni, tàbí (mojẹpe rẹ Ọlọhun fún iṣẹ ìjọsìn Hajj) tí o ba jẹ pé ẹni tí o fẹ se ìjọsìn Hajj nìkan, tàbí (mojẹpe rẹ Ọlọhun fún ìjọsìn Hajj àti Umrah) tí o ba jẹ pé ẹnití o fẹ se méjèejì papọ lẹẹkan ṣoṣo).

Tí o ba jẹ pé ẹni tí ó fẹ gbé harami ba nbẹrù idiwọ kan tí o le kọ di láti má parí ìjọsìn rẹ o lẹtọ fun kí o se majẹmu nígbàtí o ba fẹ bẹrẹ ìjọsìn pẹlu gbígbé harami tí yóò wa sọ bayi pé: (.....tí nkan kan ba di mi lọwọ tàbí o dá mi dúró níbi tí Mo ba ṣe e dé náà ni máa bọra silẹ) gbogbo ìgbàtí o bá se majẹmu tí nkan tí kò jẹ kí o parí rẹ wa sẹlẹ si i tí kò jẹ kí o parí rẹ, ibi tí o ba ṣe e dé náà ni yóò ti parí rẹ, kòsi sí ẹsẹ kan kan fun un.

Lẹyìn náà yóò ṣe gbólóhùn ijẹpe Ọlọhun: (Mojẹpe rẹ Ọlọhun, mojẹpe rẹ Ọlọhun, mojẹpe rẹ Ọlọhun kò sí orogún pẹlu rẹ mojẹpe rẹ, dájúdájú ọpẹ ati idẹra tirẹ Ọlọhun niiṣe àti ọlá tàbí ìkápá, kòsí orogún tàbí ẹnikejì fún irẹ Ọlọhun)[5], Ọkunrin yóò gbé oun rẹ soke láti wí i, bẹẹ ni obìnrin náà yóò gbé oun s'oke níbi tí kò ba sí awọn àjòjì ni ọdọ rẹ, o lẹtọ fún ẹni tí o gbé harami láti máa se gbólóhùn ijẹpe Ọlọhun lọpọlọpọ ìgbà tí isesí rẹ bati yí padà, tàbí ìyípadà àsìkò lapejuwe tí o ba gun òke tàbí tí o ba sọkalẹ, gbogbo ìgbàtí òru batiru àti tí ọsan ba ti dé. (5) ìtumọ gbólóhùn eniyan pé: (mojẹpe rẹ) o túmọ sí pé ijẹpe fún irẹ Ọlọhun oluwa, ijẹpe latun jẹpé, ìtumọ rẹ n'ipe ijẹpe ọmọ ènìyàn fún Olúwa rẹ ati iduro ṣinṣin rẹ lórí itẹle aṣẹ rẹ "dájú dájú gbogbo ọpẹ àti idẹra tirẹ Ọlọhun nii se koda àti ìkapá ọlá" "ọpẹ tàbí ìyìn ni riroyin ẹni tí a nroyin pẹlu pípé àti ìfẹ àti titobi tí a ba paara rẹ yóò di iyìn, àti pé idẹra ni oun tí Ọlọhun nṣe fún awọn ẹrú rẹ ninu oore bí kí wọn rí nkan tí wọn wa àti kí o sọ wọn kúrò níbi nkan tí kò wù wọn, ọrọ rẹ tí o sọ pé: "Àti ọlá ìtumọ rẹ nipe ìkápá ọlá tirẹ Oluwa ni Ọlọhun mimọ ní Fún ti Ọlá rẹ ga jùlọ nìkan ni o ní ìkápá ọlá, àti gbólóhùn rẹ tí o sọ pé: (kòsí orogún fún ọ) ìtumọ rẹ n'ipe enikan o ba ọ kẹgbẹ níbi nkan tí o da wa lọtọ fún Ọlọhun tí O gbọngbọn tí O tobi julọ, nínú awọn ìròyìn rẹ tí o ti pé, nínú rẹ náà ni ijẹ ọkan ṣoṣo rẹ nibi ìkápá ọlá àti dídá ẹdá àti ìdarí ètò aye, àti ilẹtọ sí ìjọsìn fún ní òun nìkan ṣoṣo. Mojmuu'l Fataawa wa Rasail Al-Huthaimin (Apapọ ìfèsì sí Ibeere ọrọ ẹṣin àti awọn ọrọ akansọ tí o jẹ ti oní mimọ Al-huthaimin (96/22) ni soki.

Wiwi gbólóhùn ijẹpe Ọlọhun ni o jẹ ilana òfin ẹṣin níbi ṣíṣe ìjọsìn Umrah láti ìgbà tí a ba tí gbé Arami titi tí a o fí bẹrẹ irọkirika ile Ọlọhun, níbi iṣẹ ìjọsìn Hajjj ṣíṣe, yóò bẹrẹ láti ìgbà tí a ba tí gbé Arami titi aa fi bẹrẹ sísọ oko Haqabah ni ọjọ Ọdun.

O pan dandan fún ẹni tí nṣe ìjọsìn Umrah lọwọ kí ọ ṣọra láti má le kòsí ọkan nínú awọn nkan tí wọn se leewọ fún ẹni tí nṣẹ Umrah lọwọ kí o má baa ba ṣíṣe ìjọsìn náà jẹ fún un titi yoo fi pari rẹ.

Ẹkẹrin: Awọn nkọn tí wọn se leewọ nígbàtí a ba gbé Arami

Awọn nkan tí wọn se leewọ nígbàtí a ba gbé Arami ni:

1. Gígé irun tàbí fifa irun tàbí fí fa irun tu láti ibì èyí k'eyi ààyè nínú ara rẹ.

2. Gigee gbogbo eekana ọwọ tàbí ti ẹsẹ, tàbí gígé diẹ nínú rẹ.

3. Fífi nkankan borí, gẹgẹ bí fìlà akẹtẹ, tàbí fila lasan, àti lawani, tàbí fífi aṣọ isolerun sí orí, tàbí kí a fi inuju tàbí suwẹta tàbí páálí tàbí nkan mii sí orí èyí tí o le fi bo ori, ìdájọ yi da wa fún Ọkùnrin nìkan Lai ko obìnrin sinu.

4. Wíwọ aṣọ ti a nwọ tẹlẹ tí wọn ti ge sí dédé aara; pẹlu Irisi rẹ tí a ti ba saaba, gẹgẹ bí: aṣọ tí wan tí ge tí wan sí ran, àti sókótó, àti buba, àti ibọsẹ méjèjì, àti ibọwọ méjèjì, eleyi da wa fún Awàn ọkùnrin nìkàn, lai ko awọn obìnrin sinu, nitoripe wan tí kọ fún awọn obìnrin:

A- Láti wọ ìbòjú àti gbogbo nkan tí o ba farajọ ìbòjú, ṣugbọn o jẹ ọranyàn fún obìnrin ki o bo ojú rẹ nigbati o ba tí wa pẹlu awọn ọkunrin tí wan kii see abeewọ rẹ pẹlu ìbòjú tí o tí nlo bo ojú, kọda kí ìbòjú naa kan ojú rẹ, kò lẹtọ fún nínú òfin ẹṣin fún láti gbé iweri and ebibo kan sí orí rẹ pẹlu erongba pé kí ebibo má baa kan loju nítorípé kò sí ẹrí kankan tí o fọwọ sí ìbámu rẹ ni ìlànà òfin esin.

B- Wíwọ ibọwọ sí ọwọ mejeji, o sí di dandan fún kí o bo ọwọ rẹ méjèjì nígbàtí o ba wa níbi tí awan ọkunrin àjòjì wa, pẹlu fífi ọwọ rẹ sínú aṣọ gbarere jalibaba rẹ.

5. Lílo lọfinda sí ará tàbí sí bí aṣọ arami rẹ.

6. Pipa eranko orilẹ, tàbí di dẹ ẹ lọde láti pàá kọda bí o tilẹ rí i pa.

7. Itọrọ iyawo yala fún ará rẹ tabi fún ẹlòmíràn.

8. Ṣíṣe ita kókó iyigi tí ìfẹra ẹni laarin ọkùnrin àti obinrin.

9. Ifaranura papọ láàrin ọkọ àti aya lai barawon ni nkan pọ; bíi kí won fi enu kọra wọn, àti igbara wọn mú pẹlu èrò adùn ará.

10. Ibalopọ tọkọtaya, òun ni kí wọn bara wọn sun.

***

Ẹlẹkaarun: bí a se nse irọkirika ile Ọlọhun.

Tí ẹni tí o dàníyàn iṣẹ Hajj tàbí Umrah (ẹni tí o gbé arami) ba wọ́ inú mosalasi won se ni ìlànà fún kí o ti ẹsẹ ọtun rẹ síwájú láti wọ inú mọsalasi kí o si máa ka ádùrá wíwọ inú mọsalasi, nínú awon ádùrá tí o lalaafia tí o sì f'ẹsẹ múlẹ tí o wa ye nípa rẹ ni kí o sọ pé: mọ pe Ire Ọlọrun Allah ṣi awon ilẹkun aanu rẹ fún mí" yóò máa se ádùrá yí tí o ba fẹ wọ èyí k'eyi mosalasi kii se mọsalasi ọwọ (Ka'abah) nìkan.

Tí o ba fẹ bẹrẹ láti máa rọkirika ilé Ọlọhun nígbà naa ni yóò pakaja aṣọ arami rẹ, bí a se má npakaja n'ipe kí o fi àárín aṣọ ibora rẹ sí abẹ abiya rẹ ọtún kí etiko aṣọ rẹ méjèjì sí wa lórí ejika rẹ tí òsì, tí o ba pari irọkirika ile Ọlọhun tán yóò da aso ibora rẹ pada si bí ọ se wa tẹlẹ síwájú kí o to bẹrẹ irọkirika ile Ọlọhun, nítorípé níbi irọkirika ile Ọlọhun nìkan ni ipakaja aṣọ arami tí ma nwaye.

Lẹyìn náà ni yóò gbà ibí òkúta dudu lọ tí yóò sí fí ọwọ rẹ ọtún kan tí yóò sí fí ẹnu kòó, tí kò bà rọrun fún un láti fí ẹnu ko o yóò fí ọwọ rẹ ba a, bẹẹ ni yó fí ẹnu kòó ọwọ náà, tí kò ba rọrun fun un láti fi ọwọ ba a yóò wa nkán nkán sí gẹgẹ bí pọpa, tàbí nkán mii, tí yóò sí fi ẹnu ko o, tí kò ba rọrun fún un bẹ, yóò kojú sí òkúta dúdú náà yóò sí náà ọwọ rẹ si lẹkan náà Lai ni fí ẹnu kòó, èyí tí o dára jù ni kí o má se ìdí funfun pẹlu awon eniyan, ki won le mọn baa kó inira ba ki óun na má ko inira ba awon eniyan.

Nígbàtí o ba fẹ fí ọwọ kan okuta tàbí tí o ba fẹ nọka sí yoo so pe: (Allah Ọlọhun lọ Tobi julọ)

Lẹyìn bẹ ni yóò gba apá ọtun yóò fi mọsalasi sí apá òsì rẹ, tí o ba de ibí Origun tí Al-yamani yóò fọwọ kan Lai ni fi ẹnu kòó, tí kò ba rọọ lọrun láti ṣe bẹ kí o má se se idifun fún láti de bẹ, bẹ koni tọkasi láti ọọkán.

Láàrin orígun Al- Yamani àti òkúta dúdú ni yóò tí má sọ bayi pé: (Irẹ Olúwa wa se daada fún wa láyé bee sini kí o se daada fún wa ni ọrun pẹlu àti pé kí o sọ wa ni bi ìyá ina).

Gbogbo ìgbà tí o ba ti rekoja lẹgbẹ òkúta dúdú náà ni yóò máa tọka si pẹlu ọwọ rẹ tí yóò sí máa sọpe: (Allahu Ọlọhun ni o tobi julọ).

Yóò sí máa ṣọ eyi tí o ba wù nínú idarukọ Ọlọhun àti ádùrá àti kíkà Al-qur'an ni bí irọkirika ile Ọlọhun tí o sẹku.

Nínú ìlànà anọbi - kí ikẹ Ọlọhun àti ọlá Rẹ máa ba a - ni kí o máa ṣe Ramal ni awọn irọkirika mẹta akọkọ, itumọ Ramal nipe ki o maa rin ni kiakia pẹlu awọn igbesẹ kukuru, ṣugbọn nibi awọn irọkirika mẹrin yoku, ko ni se ramal nibẹ, yoo maa rin gẹgẹ bi aṣa rẹ ni.

Ti o ba parí irọkirika ile Ọlọhun tan yóò bọ sí bí ààyè ìdúró anọbi Ibrahim tí yóò sí ka: (.....kí ẹ ya mú ààyè ìkìrun níbi ibuduro anọbi Ibrahim....), [Al-baqarah: 125] Lẹyìn náà yóò kirun raka méjì lẹyìn ibuduro anọbi Ibrahim, tí o ba rọrun bẹẹ kí o kí raka méjèjì ni èyí k'eyi ààyè nínú mọsalasi, níbi raka alakọkọ ni yóò tí ká: {Sọ pé mò pé ẹyin alai gbagbọ wọnyi} [Al-kaafirun:1] Yóò sika lẹyìn ọgbà ọrọ Fatiah níbi raka ẹlẹkeji: (Sọ pé Oun ni Allah Ọlọrun ọkan ṣoṣo). [Al-iKhlas: 1]

Ẹlẹkẹfa: Bí a se máa se ipọsẹsẹ:

Ti o ba ti pari irọkirika ile Ọlọhun àti kìkì Irun raka méjì lẹyìn rẹ yoo jáde lọ sí ìbi tí yóò tí se ipọsẹsẹ tí o ba ti sunmọ òke sọfa yóò ká: (Dájúdájú Sọfa àti Marwah wa nínú awọn ààyè apẹrẹ ẹṣin Ọlọhun....) Lẹyin naa yio sọ pe: "máa bẹrẹ pẹlu nkán tí Ọlọrun fí bẹrẹ" [6] [6] Muslim ni o gba a wa pẹlu ounka (1218).

Lẹyìn náà ni yóò gùn orí òkè Sọfa lọ titi yóò fí máa wo Kaabah lọọkan tàbí kí o wa ni ọgangan rẹ tí yóò sí dájú kọ, yóò sí wí gbólóhùn imú Ọlọrun ní ọkàn ṣoṣo, yóò sí gbé titobi fún, tí yóò sí sọ bayi pé: "kòsí ẹnikankan tí o yẹ kí a fí ìjọsìn fún àyàfi Allah Ọlọrun ní kàn ṣoṣo lai sí orogún pẹlu rẹ, tí ẹ ní gbogbo ọlá ati ìkápá, bẹẹ ni tí ẹ ní gbogbo iyìn àti ọpẹ, òun sí ní o ní ìkápá,lórí gbogbo nkán pátá pátá, kòsí ẹnikan kan tí o yẹ kí a fí ìjọsìn fún àyàfi Allah Ọlọrun ní kàn ṣoṣo, òun ni O pé adeunh rẹ, o sí ran ẹrú rẹ lọwọ lohùn nìkan ṣoṣo, o sí ṣẹgun awan ìjọ ọmọ oògùn ni oun nìkan ṣoṣo, lẹyìn náà ni yoo se ádùrá láàrin bẹ, yoo se ádùrá yí ní ẹmẹta [7]. [7] Musilim lo gba wa pẹlu ounka: (1218).

Lẹyìn náà ní yóò sọkalẹ láti Orí Sọfa wa sí Marwah ní ẹni tí nrín, tí o ba tí dé ibì aasia alawọ ewé yóò pọ ṣẹṣẹ ní èyí tí o lagbara, tí ba dé ibì aasia alawọ ewe ẹlẹkeji yóò rìn gẹgẹ bí o se man rìn, kòsí nínú ìlànà ẹṣin fún obìnrin láti máa sáré rìn níbi ipọsẹsẹ náà.

Ti o ba ti dé Marwah won tí se ní ìlànà ẹṣin pé kí o se iru nkán tí o se ni oke Sọfa lórí òkè Marwah náà (àpapọ ọrọ tí o wa ni onka ẹlẹkeji 2).

Lẹyìn náà ní yóò Sọkalẹ láti Orí Marwah wa sí Sofa ní ẹni tí nrín, tí o ba tí dé ibì aasia alawọ ewé yóò pọ ṣẹṣẹ ní èyí tí o lagbara, tí ba dé ibì aasia alawọ ewe ẹlẹkeji yóò rìn gẹgẹ bí o se man rìn níbi isesi rẹ.

Bayi ni yóò ṣe máa ṣé titi yóò fi pari ipaara ìrìn ipọsẹsẹ náà ni ẹẹmeeje, lilọ láti Sọfa lọsí Marwah jẹ ipaara ẹyọkan, bẹẹ ni ipada rẹ láti Marwah sí Sọfa naa tún jẹ ipaara mí.

Yóò sí máa so ìrántí Ọlọhun àti ádùrá àti kíkà Quran ní èyí tí o ba wù.

Ẹlẹẹkeji: Bí a se má nfa Irun àti gigẹrun.

Ti ẹni tí o nṣe Umrah ba tí pari irọkirika rẹ àti ipọsẹsẹ rẹ o tí di dandan ni fún láti kí o fa Irun orí rẹ tàbí kí o gẹ tí o bà jẹ pé okùnrin ni, nínú ìlànà anọbi ni ki fifa Irun tàbí gigẹẹ kárí gbogbo orí ni.

Kí a fà Irun orí dáa o sí lọla jù kí a gẹ lọ, ayaafi tí o ba ṣepe àsìkò Hajj tí sun mọn nígbàtí kò ní sí ìgbà láàyè kí irun orí wù padà, àti pé dájú dájú èyí tí o lọla jù ni kí a daa mọn lórí gigẹ irun.

Ṣugbọn obìnrin ni tiẹ òun yóò ge irun rẹ ní ateeti (ẹgbẹgbẹ) niwanba orí ika ọwọ.

Ṣugbọn ẹni tí o gbé Arami láti ṣe ìjọsìn Hajj nìkan tàbí kí o pa Hajj papọ mọ Umrah kò ni mú nkankan kúrò ninú Irun rẹ titi yóò fí di ọjọ ọdun lẹyìn tí o ba tí juko Jamrah tán.

Pẹlu bayi yóò jasi pe ẹni tí nse Umrah tí parí ìjọsìn Umrah rẹ, bẹẹ ni ẹni tí o se Hajj àti Umrah papọ tí o bo arami kí asiko Hajj to to, (Al-Mutamotihu) oti parí iṣẹ ìjọsìn Umrah rẹ.

Bi a ṣe n ṣe hajj

Alakọkọ: Dída àníyàn iṣẹ Hajj pẹlu gbígbé arami:

Ìlànà anọbi tí o wa fún ẹni tí o fẹ se ìjọsìn Hajj ni kí o bẹrẹ àníyàn Hajj (gbígbé arami) ni àsìkò iyalẹta ni ọjọ kẹjọ nínú oṣù Dhul Hijjah láti ààyè èyí tí o ti fẹ gbéra fún Ìjọsìn Hajj, tí o ba jẹ pé o wa ni ilú Makkah tàbí ibi tí kii ṣe awọn ààyè igbe Arami, tí kò bari bayi ayaafi kí o gbé aṣọ Arami rẹ níbi awọn ààyè tí wọn ti má ngbe e tí ó bá ré kọja níbẹ .

Irú nkan tí o se fún gbígbé arami fún Umrah náà ni yóò ṣẹ fún gbígbé Arami tí Hajj náà; bíi kí o wẹ, kí o sì lo lọfinda, àti Irun kiki, yóò si da aniyan (mímú èrongbà jade) fún ibẹrẹ iṣẹ Hajj èyí tíí se gbígbé Arami, tí yóò si máa wi gbólóhùn ijẹpe Ọlọhun, bí a se nwi gbólóhùn ijẹpe Ọlọhun níbi Umrah náà ni a o se wi níbi tí Hajj ṣíṣe ayaafi pé kí o sọpe Mojẹpe rẹ Ọlọhun fún ìjọsìn Hajj ṣíṣe dipọ kí o sọ pé mojẹpe rẹ Ọlọhun fún ìjọsìn Umrah.

Tí o ba se pé onbẹru idiwọ kan tí o le má jẹ́ kí o parí ìjọsìn rẹ, o lẹtọ fún kí o da monjẹmu nígbàtí o ba fẹ dàníyàn ìjọsìn náà pẹlu gbígbé Arami, kí o sọ bayi pé : (••• tí inkan kan ba dimi lọwọ, níbi tí mo ba baa dé náà ni máa ti parí iṣẹ ìjọsìn mi) nígbàtí o ba tí se monjẹmu yí tí nkan kan ba wa di lọwọ láti má le parí rẹ, o lẹtọ fun láti bọra silẹ fún ìparí iṣẹ Hajj rẹ, bẹẹ ni kosi ẹsẹ kankan fun un.

Lẹyìn náà ni yóò máa wí gbólóhùn ijẹpe Ọlọhun lọpọ lọpọ pé: (Irẹ Ọlọhun mojẹpe rẹ, Irẹ Ọlọhun mojẹpe rẹ, kòsí orogún fún Irẹ Ọlọhun, ani iwọ nìkan Ni mọ jẹpé, dajudaju ọpẹ ati ikẹ ati ìkápá ọlá tirẹ Ọlọhun nìkan niiṣe, kòsí orogún kan fún irẹ Ọlọhun), ọkunrin aa gbé òun rẹ sókè láti wí i, bẹẹ ni kí obìnrin náà se bẹẹ nígbàtí kò ba sí níbi tí awọn ọkunrin àjòjì wà, o lẹtọ fún ẹni tí nṣe Hajj to gbé Arami kí o maa wi gbólóhùn ijẹpe Ọlọhun yí ní ọpọlọpọ ìgbà tí ìsesí àti asiko ba tí nyi pada bii kí o fẹ gun ààyè tí o ga, tàbí sísọkalẹ síbi ààyè tí o lọ le, bẹẹni tí òru ba wọlede, tàbí kí ilẹmọ.

Wiwi gbólóhùn ijẹpe Ọlọhun ní o wa ni ìbámu sí ìlànà òfin ẹṣin láti ìgbà tí a ba tí gbé Arami titi yóò fi di ìgbàtí a ba bẹrẹ si ni ju oko Haqabah ni ọjọ Ọdun.

O pan dandan fún ẹni tí nṣe ìjọsìn Umrah lọwọ kí ọ ṣọra láti má le kosi ọkan nínú awọn nkan tí wọn se leewọ fún ẹni tí nṣẹ Umrah lọwọ kí o má baa ba ṣíṣe ìjọsìn náà jé fún un.

•••

Ẹlẹẹkeji: Sisùn láti alẹ mọjumọ ni Muna:

Lẹyin bẹẹ o wa nínú ìlànà anọbi fún ẹni tí nṣe ìjọsìn Hajj pé kí ọ jáde lọsí muna ni ọjọ kẹjọ nínú osù Dhul-hijjah; kí o lè kí Irun ọsán (Zhuri) àti Irun irọlẹ (Asr) àti Irun aṣalẹ (Magrib) àti Irun Akisun (Ishai) àti irun ìdaji (Fajr) ni ẹdinku lai ní kii papọ, nítorípé Anọbi kí ikẹ Ọlọhun àti ọlá Rẹ máa ba a má nse ẹdinku irun rẹ ni muna lai kii lapapọ.

Ẹlẹkẹta: Diduro àti wíwà ni Arafah àti sísun ní Muzdalifah:

Nígbàtí oòrùn bati yọ ni ọjọ kẹsan tii ṣe ọjọ Harafah, yóò rìn láti Mina lọ sí Harafah, yóò sọkalẹ sí ààyè Namrah titi oòrùn yóò fí yẹ kúrò ní àtàrí ti o ba rọrùn fún un, tí kò ba ri i ṣe bẹ kòsí aburú níbẹ, nítorípé sísọkalẹ sí Namrah jẹ ìlànà anọbi.

Tí oòrùn bati yẹ kúrò latari yóò kí Irun osan (Zhuri) àti Irun irọlẹ (Asr) ní méjì méjì (rakah méjì méjì), yóò si kí méjèjì pọ ni àsìko irun Zhuri gẹgẹ bí anọbi kí ikẹ Ọlọhun àti ọlá Rẹ máa ba a se se.

Lẹyìn náà yóò wa fí asiko lẹ fún ìrántí àti idarukọ Ọlọhun àti Adura ṣíṣe lẹyìn irun, pẹlu idirebe sí Ọlọhun tí o gbọngbọ́n tí o tobí julọ, kí o si beere nkan tí o ba fẹ ni ẹni tí yóò gbé ọwọ rẹ mejeeji sókè ni ẹni tí yóò dájú kọ ibudajukọ (gabasi).

Èyí to pọ jù nínú ádùá tí anọbi - kí ikẹ Ọlọhun àti ọlá Rẹ máa ba a - sabà nṣe púpọ jù ni ààyè ibuduro nla naa ni: "kòsí ẹni kankan tí o lẹtọ sí ijọsin ayaafi Allah (Ọlọhun) nìkan ṣoṣo tí kòsí orogún pẹlu rẹ, tírẹ ní ìkápá ọlá bẹẹ sini òunh ni o ní ọpẹ àti iyìn, òunh ni o ní ìkápá lórí gbogbo nkán".

Tí o ba rẹ ẹ, tí o si fẹ láti se faaji pẹlu awọn iyokù rẹ pẹlu biba wọn sọrọ ni awọn ọrọ ti o sanfaani tàbí kíkà nínú awọn tira tí o wúlò pàtàkì jùlọ èyí tí o nii ṣe pẹlu òun to rọ mọn apọnle Ọlọhun àti awọn ọrẹ rẹ topọ; kí abala irokan ọọre Ọlọhun ní ọjọ náà le ni agbára, eleyii daa bẹẹ, lẹyìn náà yóò padà síbi idirebe síwaju Ọlọhun àti ikepe Ọlọhun, ki o si se ojukokoro lati ṣe adura daada ni ipari ọsan, nítorípé adura tí o loore jù ni adura tí a se ní ọjọ Harafah.

Nígbàtí òrun bati wọ tan ni ọjọ Harafah ni yóò lọ sí Muzdalifah.

Tí o ba dé ibẹ tan yóò kí irun Magrib ni rakah mẹta, yóò si kí irun Akisun (Ishai) ni rakah méjì tí yóò si kí wọn ni apapọ.

Tí ìbẹrù ba wa fun pé òun kò ní tí dé Muzdalifah àyàfi lẹyìn ìdajì òru yóò kirun náà, ko da kí o to de Muzdalifah, kò lẹtọ fún un láti lọ irun lára di ẹyin ìdajì òru.

Yóò wa sun ni Muzdalifah di aarọ, tí alufajari ba ti yọ kí o kirun aarọ (Fajr) ni kia kia pẹlu irun pipe àti igberun dúró.

Lẹyìn náà ní yóò gbà ààyè ọwọ lọ, yosi mú Ọlọhun ní ọkan ṣoṣo yóò si gbé títóbi fún Ọlọhun yóò si beere nkan tí o ba fẹ lọdọ Ọlọhun titi ilẹ yóò fi mọn dàada, tí kò ba rọrun fún un láti lọ sí ààyè ọwọ yóò ṣe adua ni ààyè ti o wa; nitori ọrọ anabi - ki ike Olohun ati ola Re maa ba -: "mo duro ní ààyè yí níbi àti àkójọ papọ gbogbo rẹ nI ààyè ìdúró" [8], Nígbàtí o ba nse ìrántí Ọlọhun àti adua lọwọ yóò dájú kọ ibudajukọ ni ẹni tí yóò gbé ọwọ rẹ mejeeji sókè. [8] Abu Daud logba wa pẹlu ounka (1936).

Ẹlẹkẹrin: Awọn iṣẹ ìjọsìn ọjọ Ọdun:

Ti ilẹ bati mọ daada yóò gbé ra láti Muzdalifah láti darí sí Muna kí oòrùn toyọ, tí o ba dé ààyè tí wọn npe ni ọgbun koto Muhassar yóò yara rìn daada.

Tí o ba dé Múná yóò lọ ju oko Haqabah, òhun ni èyí tí o gbẹyin tí o tẹle Makkah, awọn òkúta keekeeke meje tí yóò jù tẹle rawọn ni ọkọọkan, òkúta kọọkan naa yóò kere bí oro ọmọ dabidun, tí yóò si máa gbé títóbi fún Ọlọhun pẹlu jiju òkúta k'ọkan.

Lẹyìn náà ni yóò pa ẹran ìjọsìn rẹ tí o ba rọọ lọrùn láti ṣe bẹ.

Lẹyìn náà ni yóò fa irun ori rẹ tàbí kí o gẹ tí o ba jẹ ọkunrin, kí o faa lọ dáa jù, ṣugbọn obìnrin wọn se ni ìlànà òfin ẹṣin fún un pé kí o get irun rẹ kí o má se fa.

Tí o ba ti jù òkúta tan tí o si fa orí rẹ, oti lẹtọ ibọra silẹ ìparí iṣẹ hajj ti akọkọ, gbogbo nkan ni yóò di etọ fún un ayaafi pé kò ni le sunmọ ìyàwó rè.

Lẹyìn náà yóò bosi Makkah tí yóò lọ se irọkirika ile Ọlọhun fún tí idari padà (Tọwaful - Ifadọh) lẹyìn náà yóò se ipọsẹsẹ láàrin Sọfa àti Marwah fún ti ìjọsìn Hajj tí o ba jẹ pé o jẹ ẹni tí nṣe Hajj ibọ Arami silẹ lẹyìn Umrah (Tamattu') tàbí o jẹ ẹni tí o da Hajj nìkan se, tàbí ẹni tí o pa Umrah papọ mọ Hajj lẹkan náà tí o já sipe koti se ipọsẹsẹ rẹ lẹyìn tí o kọkọ se irọkirika dide sí Makkah fún ìjọsìn Hajj, o lẹtọ fún un láti sọ irọkirika ile Ọlọhun rẹ ati ipọsẹsẹ rẹ di òru tàbí ọjọ Kejì, ni ibamu sí bí ọ ba se rọrun fún un.

Ẹlẹkaarun: awọn iṣẹ ìjọsìn awọn ọjọ igun ẹran

Tí o ba ju oko tan tí o si fa irun tí o si rọkirika ilé Ọlọhun, tí o si ti se ipọsẹsẹ láàrin Sọfa àti Marwah tan, o ti parí iṣẹ ìjọsìn Hajj tan yanyan, gbogbo nkan si ti di etọ fún débi obìnrin.

Yóò wa padà sí Múná yóò wa sun níbẹ ni ọjọ kọkànlá, ikejila àti ikẹtala tí o ba jẹ pé o fe pẹ nibẹ.

Yóò ju òkúta mẹtẹta náà nígbàtí oòrùn ba ti yẹ kúrò latari.

Yóò wa jù òkúta alakọkọ ni ọjọ kọkànlá - òhun ni ààyè òkúta tí o jinan si Makkah jù, òhun si ni o sunmọ mosalasi khaif jù, okuta náà yóò jẹ keekeeke meje tí yóò jù tẹle araawọn nik'ọkan, tí yóò si máa gbé titobi fún Ọlọhun níbi jiju òkúta k'ọkan, lẹyìn náà ni yóò bọ síwájú diẹ, tí yóò se adua itọrọ nkan tí o ba wù fún igba pipẹ, tí o ba soro fún un láti dúró pẹ fún adua, yóò ṣe eyi ti o rọrun fún un koda bí o se diẹ, nítorí ki itẹle ìlànà anọbi le waye.

Lẹyìn náà ni yóò jù oko ti aarin bákanáà, bẹẹ ní yóò se ádùá lẹyìn rẹ.

Lẹyìn naa yóò ju òkúta tí 'aqabah bakan náà, o kàn jẹ pé tí o ba ti ju u tan, yóò pẹyinda ni lai se ádùá kàn kan.

Lẹyìn náà ni yóò ju awọn òkúta ni ọjọ Kejìlá gẹgẹ bí ti ọjọ kọkànlá; tí o ba parí jiju awọn òkúta náà, tí o ba wu u, yoo yàrá láti kuro Múná.

Tí o ba si wu u yoo lọra, yoo sun níbẹ ni oru ọjọ kẹtala, yoo si lọju oko mẹtẹta lẹyìn ti òrun ba yẹ kuro latari gẹgẹ bí a ti se alaye rẹ kọja, kí o lọra yii ni o lọla jùlọ.

Kìí se dandan ni kí o lọra di ọjọ kẹtala ayaafi tí oòrùn bà tí wọ ni ọjọ Kejìla tí o si wa ni Múná; tulaasi ni kí o lọra titi yóò fi ju òkúta mẹtẹta lẹyìn ti òrun ba tiyẹ kúrò ní àtàrí.

Ṣugbọn tí oòrùn bati wọ ba ní Múná ni ọjọ Kejìlá lai se pẹlu amanmọ se rẹ bii kí o se irin-ajo kí o si gun mọto sugbọn o pẹ latara sunkẹrẹ-fakẹrẹ awon ọkọ ati bẹẹbẹẹlọ, dajudaju kii se dandan ni fún ki o sun Muna, nítorípé pipẹ rẹ titi di wiwọ òòrùn kii se pẹlu atọkan rẹ wa.

Ẹlẹkẹfa: Irọkirika ti idagbere:

Tí o ba fẹ jáde padà lọ sí ilu rẹ láti Makkah koni tii jáde ayaafi kí o se irọkirika ile Ọlọhun fún idagbere.

Ayaafi obinrin tí nṣe nkan osu àti ẹjẹ ibimọ lọwo, ṣíṣe irọkirika idagbere kii se dandan lórí awọn mejeeji, kòsi lẹtọ fún wọn láti lọ dúró níbi ojú òná mọsalasi ọwọ fún idagbere: nítorípé kòsí ẹri kan kan fun láti ọdọ anọbi - ki ikẹ Ọlọhun àti ọla Rẹ máa ba -.

Yóò fí irọkirika ti idagbere se nkan tí yóò se gbẹyin tí yóò sí rí ile Ọlọhun gbẹyin nígbàtí o ba fẹ ṣe Irinajo padà si ìlú rẹ.

Lẹyìn tí o ti dagbere tán tí o ba wa tun dúró díẹ láti retí awọn ikọ kan tàbí láti gbé àpò rẹ tàbí láti ra nkan ti o fẹ ni oju-ọna rẹ kosi laifi nibẹ, koni tun Tawaaf se ayaafi ti o ba ni lọkan lati sun irin-ajo rẹ siwaju, bi ki o fẹ rinrinajo ni akọkọ ọsan ki o wa se irọkirika ti idagbere, lẹyin naa ki o tun wa lọ lara di ipari ọsan fun apejuwe, yoo di dandan fun lati tun irọkirika se ki o le jẹ ikẹhin idagbere rẹ pẹlu ile Ọlọhun.

Kí Ọlọhun bawa se ikẹ ati igẹ fún Anọbi wa Muhammad.