42 : 40
وَجَزَٰٓؤُاْ سَيِّئَةٖ سَيِّئَةٞ مِّثۡلُهَاۖ فَمَنۡ عَفَا وَأَصۡلَحَ فَأَجۡرُهُۥ عَلَى ٱللَّهِۚ إِنَّهُۥ لَا يُحِبُّ ٱلظَّٰلِمِينَ
Ẹ̀san aburú sì ni aburú bí irú rẹ̀. Ẹnikẹ́ni tí ó bá sì ṣàmójúkúrò, tí ó tún ṣàtúnṣe, ẹ̀san rẹ̀ wà lọ́dọ̀ Allāhu. Dájúdájú (Allāhu) kò nífẹ̀ẹ́ àwọn alábòsí.
Explanation & meanings · 1
- Kíyè sí i, gbólóhùn yìí “Ẹ̀san aburú sì ni aburú bí irú rẹ̀.” kò tako sūrah Fussilat; 41:31. Ìdí ni pé, gbígba ẹ̀san lára alábòsí tàbí gbígba ààrọ̀ kò sọ pé mùsùlùmí kò ní ẹ̀mí àforíjìn, àmọ́ ó lè má nìí agbára láti ṣàmójú kúrò fún alábòsí náà. Bí àpẹ̀ẹrẹ, kí ẹnì kan ba dúkìá mùsùlùmí jẹ́, yálà ó ṣèèsì tàbí ó mọ̀ọ́mọ̀, mùsùlùmí lè gbẹ̀san ààrọ̀ níwọ̀n ìgbà tí agbára rẹ̀ kò bá gbé àtúnṣe rẹ̀ tàbí ìràpadà rẹ̀. Kò sì níí gbà ju ohun tí wọ́n bàjẹ́.