Skip to content
فَاطِر /

Ẹsẹ 28

35 : 28
فَاطِر Àwọn Ẹsẹ 45
Súrà · فَاطِر
Yorùbá · Mikail
35 : 28

وَمِنَ ٱلنَّاسِ وَٱلدَّوَآبِّ وَٱلۡأَنۡعَٰمِ مُخۡتَلِفٌ أَلۡوَٰنُهُۥ كَذَٰلِكَۗ إِنَّمَا يَخۡشَى ٱللَّهَ مِنۡ عِبَادِهِ ٱلۡعُلَمَٰٓؤُاْۗ إِنَّ ٱللَّهَ عَزِيزٌ غَفُورٌ

Àti pé ó wà nínú àwọn ènìyàn, àwọn n̄ǹkan ẹlẹ́mìí àti àwọn ẹran-ọ̀sìn tí àwọ̀ wọn yàtọ̀ síra wọn, gẹ́gẹ́ bí (àwọ̀ èso àti àpáta) wọ̀nyẹn (ṣe yàtọ̀ síra wọn). Àwọn tó ń páyà Allāhu nínú àwọn ẹrúsìn Rẹ̀ ni àwọn onímọ̀ (tí wọ́n mọ̀ pé), dájúdájú Allāhu ni Alágbára, Aláforíjìn.

Explanation & meanings · 1
  1. Àìmọ̀kan kò ṣeé lò láti fi páyà Allāhu - subhānahu wa ta‘ālā - . Aláìmọ̀kan yóò máa ṣe àwọn kiní kàn tí ó máa lérò pé òun ń fi páyà Allāhu ni, àmọ́ tó jẹ́ pé ńṣe l’ó ń da ara rẹ̀ láàmú. Ìmọ̀ nípa Allāhu ni ènìyàn lè fi páyà Allāhu ní ọ̀nà òtítọ́ àti ní ọ̀nà ẹ̀tọ́. Ìmọ̀ náà ní àsìkò yìí ni ìmọ̀ al-Ƙur’ān àti sunnah Ànábì Muhammad - kí ìkẹ́ àti ọlà Allāhu máa bá a - .